Surah Saba with Yoruba

  1. Surah mp3
  2. More
  3. Yoruba
The Holy Quran | Quran translation | Language Yoruba | Surah Saba | سبأ - Ayat Count 54 - The number of the surah in moshaf: 34 - The meaning of the surah in English: Sheba.

الْحَمْدُ لِلَّهِ الَّذِي لَهُ مَا فِي السَّمَاوَاتِ وَمَا فِي الْأَرْضِ وَلَهُ الْحَمْدُ فِي الْآخِرَةِ ۚ وَهُوَ الْحَكِيمُ الْخَبِيرُ(1)

 Gbogbo ope n je ti Allahu, Eni ti ohunkohun t’o wa ninu awon sanmo ati ohunkohun t’o wa ninu ile n je tiRe. Ati pe tiRe ni gbogbo ope ni orun. Oun si ni Ologbon, Alamotan

يَعْلَمُ مَا يَلِجُ فِي الْأَرْضِ وَمَا يَخْرُجُ مِنْهَا وَمَا يَنزِلُ مِنَ السَّمَاءِ وَمَا يَعْرُجُ فِيهَا ۚ وَهُوَ الرَّحِيمُ الْغَفُورُ(2)

 O mo ohunkohun t’o n wonu ile ati ohunkohun t’o n jade latinu re. (O mo) ohunkohun t’o n sokale latinu sanmo ati ohunkohun t’o n gunke lo sinu re. Oun si ni Asake-orun, Alaforijin

وَقَالَ الَّذِينَ كَفَرُوا لَا تَأْتِينَا السَّاعَةُ ۖ قُلْ بَلَىٰ وَرَبِّي لَتَأْتِيَنَّكُمْ عَالِمِ الْغَيْبِ ۖ لَا يَعْزُبُ عَنْهُ مِثْقَالُ ذَرَّةٍ فِي السَّمَاوَاتِ وَلَا فِي الْأَرْضِ وَلَا أَصْغَرُ مِن ذَٰلِكَ وَلَا أَكْبَرُ إِلَّا فِي كِتَابٍ مُّبِينٍ(3)

 Awon alaigbagbo wi pe: “Akoko naa ko nii de ba wa.” So pe: “Bee ko. Emi fi Oluwa mi bura. Dajudaju o maa de ba yin (lati odo) Onimo-ikoko (Eni ti) odiwon omo ina-igun ko pamo fun ninu sanmo ati ninu ile. (Ko si nnkan ti o) kere si iyen tabi ti o tobi (ju u lo) afi ki o wa ninu akosile t’o yanju.”

لِّيَجْزِيَ الَّذِينَ آمَنُوا وَعَمِلُوا الصَّالِحَاتِ ۚ أُولَٰئِكَ لَهُم مَّغْفِرَةٌ وَرِزْقٌ كَرِيمٌ(4)

 (O maa sele) nitori ki Allahu le san esan fun awon t’o gbagbo ni ododo, ti won tun se ise rere. Awon wonyen ni aforijin ati ese alapon-onle n be fun

وَالَّذِينَ سَعَوْا فِي آيَاتِنَا مُعَاجِزِينَ أُولَٰئِكَ لَهُمْ عَذَابٌ مِّن رِّجْزٍ أَلِيمٌ(5)

 Ati pe awon t’o se ise buruku nipa awon ayah Wa, (ti won lero pe) awon mori bo ninu iya; awon wonyen ni iya eleta-elero t’o buru n be fun

وَيَرَى الَّذِينَ أُوتُوا الْعِلْمَ الَّذِي أُنزِلَ إِلَيْكَ مِن رَّبِّكَ هُوَ الْحَقَّ وَيَهْدِي إِلَىٰ صِرَاطِ الْعَزِيزِ الْحَمِيدِ(6)

 Awon ti A fun ni imo ri i pe eyi ti won sokale fun o lati odo Oluwa re, ohun ni ododo, ati pe o n se itosona si ona Alagbara, Eleyin

وَقَالَ الَّذِينَ كَفَرُوا هَلْ نَدُلُّكُمْ عَلَىٰ رَجُلٍ يُنَبِّئُكُمْ إِذَا مُزِّقْتُمْ كُلَّ مُمَزَّقٍ إِنَّكُمْ لَفِي خَلْقٍ جَدِيدٍ(7)

 Awon t’o sai gbagbo wi pe: “Se ki a toka yin si okunrin kan ti o maa fun yin ni iro pe nigba ti won ba fon yin ka tan patapata (sinu erupe), pe dajudaju e maa pada wa ni eda titun

أَفْتَرَىٰ عَلَى اللَّهِ كَذِبًا أَم بِهِ جِنَّةٌ ۗ بَلِ الَّذِينَ لَا يُؤْمِنُونَ بِالْآخِرَةِ فِي الْعَذَابِ وَالضَّلَالِ الْبَعِيدِ(8)

 Se o da adapa iro mo Allahu ni tabi alujannu n be lara re ni?” Rara o! Awon ti ko gba Ojo Ikeyin gbo ti wa ninu iya ati isina t’o jinna

أَفَلَمْ يَرَوْا إِلَىٰ مَا بَيْنَ أَيْدِيهِمْ وَمَا خَلْفَهُم مِّنَ السَّمَاءِ وَالْأَرْضِ ۚ إِن نَّشَأْ نَخْسِفْ بِهِمُ الْأَرْضَ أَوْ نُسْقِطْ عَلَيْهِمْ كِسَفًا مِّنَ السَّمَاءِ ۚ إِنَّ فِي ذَٰلِكَ لَآيَةً لِّكُلِّ عَبْدٍ مُّنِيبٍ(9)

 Se won ko ri ohun t’o n be niwaju won ati ohun t’o n be leyin won ni sanmo ati ile? Ti A ba fe, Awa iba je ki ile ri mo won lese, tabi ki A ja apa kan sanmo lule le won lori mole. Dajudaju ami kan wa ninu iyen fun gbogbo erusin, oluronupiwada

۞ وَلَقَدْ آتَيْنَا دَاوُودَ مِنَّا فَضْلًا ۖ يَا جِبَالُ أَوِّبِي مَعَهُ وَالطَّيْرَ ۖ وَأَلَنَّا لَهُ الْحَدِيدَ(10)

 Dajudaju A ti fun (Anabi) Dawud ni oore ajulo lati odo Wa; Eyin apata, e se afomo pelu re. (A pe) awon eye naa (pe ki won se bee.) A si ro irin fun un

أَنِ اعْمَلْ سَابِغَاتٍ وَقَدِّرْ فِي السَّرْدِ ۖ وَاعْمَلُوا صَالِحًا ۖ إِنِّي بِمَا تَعْمَلُونَ بَصِيرٌ(11)

 (A so fun un) pe se awon ewu irin t’o maa bo ara, se oruka-orun fun ewu irin naa niwon-niwon. Ki e si se rere. Dajudaju Emi ni Oluriran nipa ohun ti e n se nise

وَلِسُلَيْمَانَ الرِّيحَ غُدُوُّهَا شَهْرٌ وَرَوَاحُهَا شَهْرٌ ۖ وَأَسَلْنَا لَهُ عَيْنَ الْقِطْرِ ۖ وَمِنَ الْجِنِّ مَن يَعْمَلُ بَيْنَ يَدَيْهِ بِإِذْنِ رَبِّهِ ۖ وَمَن يَزِغْ مِنْهُمْ عَنْ أَمْرِنَا نُذِقْهُ مِنْ عَذَابِ السَّعِيرِ(12)

 Ati pe (A te) ategun lori ba fun (Anabi) Sulaemon, irin osu kan ni irin owuro re, irin osu kan si ni irin irole re . A si mu ki odo ide maa san ninu ile fun un. O si wa ninu awon alujannu, eyi t’o n sise (fun un) niwaju re pelu iyonda Oluwa re. Ati pe eni ti o ba gbunri kuro nibi ase Wa ninu won, A maa fun un ni iya ina t’o n jo fofo to wo

يَعْمَلُونَ لَهُ مَا يَشَاءُ مِن مَّحَارِيبَ وَتَمَاثِيلَ وَجِفَانٍ كَالْجَوَابِ وَقُدُورٍ رَّاسِيَاتٍ ۚ اعْمَلُوا آلَ دَاوُودَ شُكْرًا ۚ وَقَلِيلٌ مِّنْ عِبَادِيَ الشَّكُورُ(13)

 Won n se ise ti o ba fe fun un nipa mimo awon ile t’o dara, awon ere, awo koto fife bi abata ati awon ikoko t’o ridii mule. Eyin eniyan (Anabi) Dawud, e sise idupe (fun Allahu). Die ninu awon erusin Mi si ni oludupe

فَلَمَّا قَضَيْنَا عَلَيْهِ الْمَوْتَ مَا دَلَّهُمْ عَلَىٰ مَوْتِهِ إِلَّا دَابَّةُ الْأَرْضِ تَأْكُلُ مِنسَأَتَهُ ۖ فَلَمَّا خَرَّ تَبَيَّنَتِ الْجِنُّ أَن لَّوْ كَانُوا يَعْلَمُونَ الْغَيْبَ مَا لَبِثُوا فِي الْعَذَابِ الْمُهِينِ(14)

 Nigba ti A pase pe ki iku pa (Anabi) Sulaemon, ko si ohun ti o mu awon alujannu mo pe o ti ku bi ko se kokoro inu ile kan ti o je opa re. Nigba ti o wo lule, o han kedere si awon alujannu pe ti o ba je pe awon ni imo ikoko ni, awon iba ti wa ninu (ise) iya t’o n yepere eda

لَقَدْ كَانَ لِسَبَإٍ فِي مَسْكَنِهِمْ آيَةٌ ۖ جَنَّتَانِ عَن يَمِينٍ وَشِمَالٍ ۖ كُلُوا مِن رِّزْقِ رَبِّكُمْ وَاشْكُرُوا لَهُ ۚ بَلْدَةٌ طَيِّبَةٌ وَرَبٌّ غَفُورٌ(15)

 Dajudaju ami kan wa fun awon Saba’ ninu ibugbe won; (ohun ni) ogba oko meji t’o wa ni otun ati ni osi. “E je ninu arisiki Oluwa yin. Ki e si dupe fun Un.” Ilu t’o dara ni (ile Saba’. Allahu si ni) Oluwa Alaforijin

فَأَعْرَضُوا فَأَرْسَلْنَا عَلَيْهِمْ سَيْلَ الْعَرِمِ وَبَدَّلْنَاهُم بِجَنَّتَيْهِمْ جَنَّتَيْنِ ذَوَاتَيْ أُكُلٍ خَمْطٍ وَأَثْلٍ وَشَيْءٍ مِّن سِدْرٍ قَلِيلٍ(16)

 Won gbunri (nibi esin). Nitori naa, A ran adagun odo ti won mo odi yika si won. A si paaro oko won mejeeji fun won pelu oko meji miiran ti o je oko eleso kikoro, oko igi elegun-un ati kini kan die ninu igi sidir

ذَٰلِكَ جَزَيْنَاهُم بِمَا كَفَرُوا ۖ وَهَلْ نُجَازِي إِلَّا الْكَفُورَ(17)

 Iyen ni A fi san won ni esan nitori pe won sai moore. Nje A maa san eni kan lesan iya bi ko se alaimoore

وَجَعَلْنَا بَيْنَهُمْ وَبَيْنَ الْقُرَى الَّتِي بَارَكْنَا فِيهَا قُرًى ظَاهِرَةً وَقَدَّرْنَا فِيهَا السَّيْرَ ۖ سِيرُوا فِيهَا لَيَالِيَ وَأَيَّامًا آمِنِينَ(18)

 A si fi awon ilu kan t’o han si aarin ilu ti A ran adagun odo si ati awon ilu ti A fi ibukun si. A si seto ibuso niwon-niwon fun irin-ajo sise sinu awon ilu naa. E rin lo sinu won ni oru ati ni oju ojo pelu ifayabale

فَقَالُوا رَبَّنَا بَاعِدْ بَيْنَ أَسْفَارِنَا وَظَلَمُوا أَنفُسَهُمْ فَجَعَلْنَاهُمْ أَحَادِيثَ وَمَزَّقْنَاهُمْ كُلَّ مُمَزَّقٍ ۚ إِنَّ فِي ذَٰلِكَ لَآيَاتٍ لِّكُلِّ صَبَّارٍ شَكُورٍ(19)

 (Awon ara ilu Saba’) wi pe: “Oluwa wa, mu awon irin-ajo wa lati ilu kan si ilu miiran jinna sira won.” Won se abosi si emi ara won. A si so won di itan. A si fon won ka patapata. Dajudaju awon ami kan wa ninu iyen fun gbogbo onisuuru, oludupe

وَلَقَدْ صَدَّقَ عَلَيْهِمْ إِبْلِيسُ ظَنَّهُ فَاتَّبَعُوهُ إِلَّا فَرِيقًا مِّنَ الْمُؤْمِنِينَ(20)

 Dajudaju ’Iblis ti so aba re di ododo le won lori. Won si tele e afi igun kan ninu awon onigbagbo ododo

وَمَا كَانَ لَهُ عَلَيْهِم مِّن سُلْطَانٍ إِلَّا لِنَعْلَمَ مَن يُؤْمِنُ بِالْآخِرَةِ مِمَّنْ هُوَ مِنْهَا فِي شَكٍّ ۗ وَرَبُّكَ عَلَىٰ كُلِّ شَيْءٍ حَفِيظٌ(21)

 (’Iblis) ko si ni agbara kan lori won bi ko se pe ki A le safi han eni t’o gba Ojo Ikeyin gbo kuro lara eni t’o wa ninu iyemeji nipa re. Oluso si ni Oluwa re lori gbogbo nnkan

قُلِ ادْعُوا الَّذِينَ زَعَمْتُم مِّن دُونِ اللَّهِ ۖ لَا يَمْلِكُونَ مِثْقَالَ ذَرَّةٍ فِي السَّمَاوَاتِ وَلَا فِي الْأَرْضِ وَمَا لَهُمْ فِيهِمَا مِن شِرْكٍ وَمَا لَهُ مِنْهُم مِّن ظَهِيرٍ(22)

 So pe: “E pe awon ti e so pe (won je oluwa) leyin Allahu.” Won ko ni ikapa odiwon omo-ina igun ninu sanmo tabi ninu ile. Won ko si ni ipin kan ninu mejeeji. Ati pe ko si oluranlowo kan fun Allahu laaarin won

وَلَا تَنفَعُ الشَّفَاعَةُ عِندَهُ إِلَّا لِمَنْ أَذِنَ لَهُ ۚ حَتَّىٰ إِذَا فُزِّعَ عَن قُلُوبِهِمْ قَالُوا مَاذَا قَالَ رَبُّكُمْ ۖ قَالُوا الْحَقَّ ۖ وَهُوَ الْعَلِيُّ الْكَبِيرُ(23)

 Isipe ko si nii sanfaani lodo Allahu afi fun eni ti O ba yonda fun. (Inufu-ayafu ni awon olusipe ati awon olusipe-fun maa wa) titi A oo fi yo ijaya kuro ninu okan won. Won si maa so (fun awon molaika) pe: “Ki ni Oluwa yin so (ni esi isipe)?” Won maa so pe: “Ododo l’O so (isipe yin ti wole. Allahu) Oun l’O ga, O tobi

۞ قُلْ مَن يَرْزُقُكُم مِّنَ السَّمَاوَاتِ وَالْأَرْضِ ۖ قُلِ اللَّهُ ۖ وَإِنَّا أَوْ إِيَّاكُمْ لَعَلَىٰ هُدًى أَوْ فِي ضَلَالٍ مُّبِينٍ(24)

 So pe: “Ta ni O n pese fun yin lati inu awon sanmo ati ile?” So pe: “Allahu ni.” Dajudaju awa tabi eyin wa ninu imona tabi ninu isina ponnbele

قُل لَّا تُسْأَلُونَ عَمَّا أَجْرَمْنَا وَلَا نُسْأَلُ عَمَّا تَعْمَلُونَ(25)

 So pe: “Won ko nii bi yin leere nipa ese ti a da; won ko si nii bi awa naa nipa ohun ti e n se nise.”

قُلْ يَجْمَعُ بَيْنَنَا رَبُّنَا ثُمَّ يَفْتَحُ بَيْنَنَا بِالْحَقِّ وَهُوَ الْفَتَّاحُ الْعَلِيمُ(26)

 So pe: “Oluwa wa yoo ko wa jo papo. Leyin naa, O maa fi ododo sedajo laaarin wa. Oun si ni Onidaajo, Onimo.”

قُلْ أَرُونِيَ الَّذِينَ أَلْحَقْتُم بِهِ شُرَكَاءَ ۖ كَلَّا ۚ بَلْ هُوَ اللَّهُ الْعَزِيزُ الْحَكِيمُ(27)

 So pe: “E fi han mi na awon orisa ti e dapo mo Allahu.” Rara (ko ni akegbe). Rara se, Oun ni Alagbara, Ologbon

وَمَا أَرْسَلْنَاكَ إِلَّا كَافَّةً لِّلنَّاسِ بَشِيرًا وَنَذِيرًا وَلَٰكِنَّ أَكْثَرَ النَّاسِ لَا يَعْلَمُونَ(28)

 A o ran o nise afi si gbogbo eniyan patapata; (o je) oniroo-idunnu ati olukilo sugbon opolopo awon eniyan ko mo

وَيَقُولُونَ مَتَىٰ هَٰذَا الْوَعْدُ إِن كُنتُمْ صَادِقِينَ(29)

 Won si n wi pe: “Igba wo ni adehun yii yoo se ti e ba je olododo?”

قُل لَّكُم مِّيعَادُ يَوْمٍ لَّا تَسْتَأْخِرُونَ عَنْهُ سَاعَةً وَلَا تَسْتَقْدِمُونَ(30)

 So pe: “Adehun ojo kan n be fun yin, ti eyin ko le sun siwaju di igba kan, e o si le fa a seyin.”

وَقَالَ الَّذِينَ كَفَرُوا لَن نُّؤْمِنَ بِهَٰذَا الْقُرْآنِ وَلَا بِالَّذِي بَيْنَ يَدَيْهِ ۗ وَلَوْ تَرَىٰ إِذِ الظَّالِمُونَ مَوْقُوفُونَ عِندَ رَبِّهِمْ يَرْجِعُ بَعْضُهُمْ إِلَىٰ بَعْضٍ الْقَوْلَ يَقُولُ الَّذِينَ اسْتُضْعِفُوا لِلَّذِينَ اسْتَكْبَرُوا لَوْلَا أَنتُمْ لَكُنَّا مُؤْمِنِينَ(31)

 Awon t’o sai gbagbo wi pe: “A o nii ni igbagbo ninu al-Ƙur’an yii ati eyi t’o wa siwaju re.” Ti o ba je pe o ba ri won ni nigba ti won ba da awon alabosi duro niwaju Oluwa won, (o maa ri won ti) apa kan won yoo da oro naa pada si apa kan; awon ti won so di ole (ninu won) yoo wi fun awon t’o segberaga (ninu won) pe: “Ti ki i ba se eyin ni, awa iba je onigbagbo ododo.”

قَالَ الَّذِينَ اسْتَكْبَرُوا لِلَّذِينَ اسْتُضْعِفُوا أَنَحْنُ صَدَدْنَاكُمْ عَنِ الْهُدَىٰ بَعْدَ إِذْ جَاءَكُم ۖ بَلْ كُنتُم مُّجْرِمِينَ(32)

 Awon t’o segberaga yo si wi fun awon ti won so di ole pe: “Se awa l’a se yin lori kuro ninu imona leyin ti o de ba yin? Rara o! Odaran ni yin ni.”

وَقَالَ الَّذِينَ اسْتُضْعِفُوا لِلَّذِينَ اسْتَكْبَرُوا بَلْ مَكْرُ اللَّيْلِ وَالنَّهَارِ إِذْ تَأْمُرُونَنَا أَن نَّكْفُرَ بِاللَّهِ وَنَجْعَلَ لَهُ أَندَادًا ۚ وَأَسَرُّوا النَّدَامَةَ لَمَّا رَأَوُا الْعَذَابَ وَجَعَلْنَا الْأَغْلَالَ فِي أَعْنَاقِ الَّذِينَ كَفَرُوا ۚ هَلْ يُجْزَوْنَ إِلَّا مَا كَانُوا يَعْمَلُونَ(33)

 Awon ti won so di ole yo si wi fun awon t’o segberaga pe: “Rara! Ete oru ati osan (lati odo yin loko ba wa) nigba ti e n pa wa ni ase pe ki a sai gbagbo ninu Allahu, ki a si so (awon kan) di egbe Re.” Won fi abamo won pamo nigba ti won ri iya. A si ko ewon si orun awon t’o sai gbagbo. Se A oo san won ni esan kan bi ko se ohun ti won n se nise

وَمَا أَرْسَلْنَا فِي قَرْيَةٍ مِّن نَّذِيرٍ إِلَّا قَالَ مُتْرَفُوهَا إِنَّا بِمَا أُرْسِلْتُم بِهِ كَافِرُونَ(34)

 Ati pe A o ran olukilo kan si ilu kan ayafi ki awon onigbedemuke ilu naa wi pe: “Dajudaju awa sai gbagbo ninu ohun ti Won fi ran yin nise.”

وَقَالُوا نَحْنُ أَكْثَرُ أَمْوَالًا وَأَوْلَادًا وَمَا نَحْنُ بِمُعَذَّبِينَ(35)

 Won tun wi pe: “Awa ni dukia ati omo ju (yin lo); won ko si nii je wa niya.”

قُلْ إِنَّ رَبِّي يَبْسُطُ الرِّزْقَ لِمَن يَشَاءُ وَيَقْدِرُ وَلَٰكِنَّ أَكْثَرَ النَّاسِ لَا يَعْلَمُونَ(36)

 So pe: “Dajudaju Oluwa mi, O n te arisiki sile fun eni ti O ba fe. O si n diwon re (fun elomiiran), sugbon opolopo awon eniyan ko mo

وَمَا أَمْوَالُكُمْ وَلَا أَوْلَادُكُم بِالَّتِي تُقَرِّبُكُمْ عِندَنَا زُلْفَىٰ إِلَّا مَنْ آمَنَ وَعَمِلَ صَالِحًا فَأُولَٰئِكَ لَهُمْ جَزَاءُ الضِّعْفِ بِمَا عَمِلُوا وَهُمْ فِي الْغُرُفَاتِ آمِنُونَ(37)

 Ki i se awon dukia yin, ki i si se awon omo yin ni nnkan ti o maa mu yin sunmo Wa pekipeki afi eni ti o ba gbagbo ni ododo, ti o si se ise rere. Awon wonyen ni esan ilopo wa fun nipa ohun ti won se nise. Won yo si wa ninu awon ipo giga (ninu Ogba Idera) pelu ifayabale

وَالَّذِينَ يَسْعَوْنَ فِي آيَاتِنَا مُعَاجِزِينَ أُولَٰئِكَ فِي الْعَذَابِ مُحْضَرُونَ(38)

 Awon t’o n se ise aburu nipa awon ayah Wa, (ti won lero pe) awon mori bo ninu iya; awon wonyen ni won maa mu wa sinu Ina.”

قُلْ إِنَّ رَبِّي يَبْسُطُ الرِّزْقَ لِمَن يَشَاءُ مِنْ عِبَادِهِ وَيَقْدِرُ لَهُ ۚ وَمَا أَنفَقْتُم مِّن شَيْءٍ فَهُوَ يُخْلِفُهُ ۖ وَهُوَ خَيْرُ الرَّازِقِينَ(39)

 So pe: “Dajudaju Oluwa mi, O n te arisiki sile fun eni ti O ba fe. O si n diwon re fun elomiiran. Ati pe ohunkohun ti e ba na, Oun l’O maa fi (omiran) ropo re. O si l’oore julo ninu awon olupese.”

وَيَوْمَ يَحْشُرُهُمْ جَمِيعًا ثُمَّ يَقُولُ لِلْمَلَائِكَةِ أَهَٰؤُلَاءِ إِيَّاكُمْ كَانُوا يَعْبُدُونَ(40)

 Ni ojo ti Allahu yoo ko gbogbo won jo patapata, leyin naa O maa so fun awon molaika pe: “Se eyin ni won n josin fun?”

قَالُوا سُبْحَانَكَ أَنتَ وَلِيُّنَا مِن دُونِهِم ۖ بَلْ كَانُوا يَعْبُدُونَ الْجِنَّ ۖ أَكْثَرُهُم بِهِم مُّؤْمِنُونَ(41)

 Won a so pe: “Mimo fun O! Iwo ni Alaabo wa, ki i se awon. Rara (won ko josin fun wa). Awon alujannu ni won n josin fun; opolopo won ni won gba alujannu gbo

فَالْيَوْمَ لَا يَمْلِكُ بَعْضُكُمْ لِبَعْضٍ نَّفْعًا وَلَا ضَرًّا وَنَقُولُ لِلَّذِينَ ظَلَمُوا ذُوقُوا عَذَابَ النَّارِ الَّتِي كُنتُم بِهَا تُكَذِّبُونَ(42)

 Nitori naa, ni oni apa kan yin ko ni ikapa anfaani, ko si ni ikapa inira fun apa kan. A si maa so fun awon t’o sabosi pe: “E to iya Ina ti e n pe niro wo.”

وَإِذَا تُتْلَىٰ عَلَيْهِمْ آيَاتُنَا بَيِّنَاتٍ قَالُوا مَا هَٰذَا إِلَّا رَجُلٌ يُرِيدُ أَن يَصُدَّكُمْ عَمَّا كَانَ يَعْبُدُ آبَاؤُكُمْ وَقَالُوا مَا هَٰذَا إِلَّا إِفْكٌ مُّفْتَرًى ۚ وَقَالَ الَّذِينَ كَفَرُوا لِلْحَقِّ لَمَّا جَاءَهُمْ إِنْ هَٰذَا إِلَّا سِحْرٌ مُّبِينٌ(43)

 Ati pe nigba ti won ba n ke awon ayah Wa t’o yanju fun won, won a wi pe: “Ki ni eyi bi ko se okunrin kan ti o fe se yin lori kuro nibi nnkan ti awon baba yin n josin fun.” Won tun wi pe: “Ki ni eyi bi ko se adapa iro.” Ati pe awon t’o sai gbagbo wi nipa ododo nigba ti o de ba won pe: “Ki ni eyi bi ko se idan ponnbele.”

وَمَا آتَيْنَاهُم مِّن كُتُبٍ يَدْرُسُونَهَا ۖ وَمَا أَرْسَلْنَا إِلَيْهِمْ قَبْلَكَ مِن نَّذِيرٍ(44)

 A o fun won ni awon tira kan kan ti won n ko eko ninu re, A o si ran olukilo kan kan si won siwaju re

وَكَذَّبَ الَّذِينَ مِن قَبْلِهِمْ وَمَا بَلَغُوا مِعْشَارَ مَا آتَيْنَاهُمْ فَكَذَّبُوا رُسُلِي ۖ فَكَيْفَ كَانَ نَكِيرِ(45)

 Awon t’o siwaju won naa pe ododo niro. (Owo awon wonyi) ko si ti i te ida kan ida mewaa ninu ohun ti A fun (awon t’o siwaju). Sibesibe won pe awon Ojise Mi ni opuro. Bawo si ni bi Mo se (fi iya) ko (aburu fun won) ti ri

۞ قُلْ إِنَّمَا أَعِظُكُم بِوَاحِدَةٍ ۖ أَن تَقُومُوا لِلَّهِ مَثْنَىٰ وَفُرَادَىٰ ثُمَّ تَتَفَكَّرُوا ۚ مَا بِصَاحِبِكُم مِّن جِنَّةٍ ۚ إِنْ هُوَ إِلَّا نَذِيرٌ لَّكُم بَيْنَ يَدَيْ عَذَابٍ شَدِيدٍ(46)

 So pe: “Ohun kan soso ni mo n se waasi re fun yin pe, e duro nitori ti Allahu ni meji ati ni eyo kookan. Leyin naa, ki e ronu jinle. Ko si alujannu kan lara eni yin. Ko si je kini kan bi ko se olukilo fun yin siwaju iya lile kan.”

قُلْ مَا سَأَلْتُكُم مِّنْ أَجْرٍ فَهُوَ لَكُمْ ۖ إِنْ أَجْرِيَ إِلَّا عَلَى اللَّهِ ۖ وَهُوَ عَلَىٰ كُلِّ شَيْءٍ شَهِيدٌ(47)

 So pe: “Emi ko bi yin leere owo-oya kan, eyin le kuku lowo yin. Ko si owo oya mi (lodo eni kan) afi lodo Allahu. Oun si ni Arinu-rode gbogbo nnkan.”

قُلْ إِنَّ رَبِّي يَقْذِفُ بِالْحَقِّ عَلَّامُ الْغُيُوبِ(48)

 So pe: “Dajudaju Oluwa mi, Onimo-ikoko l’O n mu ododo wa.”

قُلْ جَاءَ الْحَقُّ وَمَا يُبْدِئُ الْبَاطِلُ وَمَا يُعِيدُ(49)

 So pe: “Ododo ti de. Iro (esu) ko le mu nnkan be, ko si le da nnkan pada (leyin to ti ku).”

قُلْ إِن ضَلَلْتُ فَإِنَّمَا أَضِلُّ عَلَىٰ نَفْسِي ۖ وَإِنِ اهْتَدَيْتُ فَبِمَا يُوحِي إِلَيَّ رَبِّي ۚ إِنَّهُ سَمِيعٌ قَرِيبٌ(50)

 So pe: “Ti mo ba sina, mo sina fun emi ara mi ni. Ti mo ba si mona, nipa ohun ti Oluwa mi fi ranse si mi ni imisi ni. Dajudaju Oun ni Olugbo, Alasun-unmo eda.”

وَلَوْ تَرَىٰ إِذْ فَزِعُوا فَلَا فَوْتَ وَأُخِذُوا مِن مَّكَانٍ قَرِيبٍ(51)

 Ti o ba je pe o le ri (esin won ni) nigba ti eru ba de ba won (ni Ojo Ajinde, o maa ri i pe), ko nii si imoribo kan (fun won). A si maa gba won mu lati aye t’o sunmo

وَقَالُوا آمَنَّا بِهِ وَأَنَّىٰ لَهُمُ التَّنَاوُشُ مِن مَّكَانٍ بَعِيدٍ(52)

 Won yoo wi pe: “A gbagbo ninu (al-Ƙur’an bayii).” Bawo ni owo won se le te igbagbo ododo lati aye t’o jinna (iyen, orun).”

وَقَدْ كَفَرُوا بِهِ مِن قَبْلُ ۖ وَيَقْذِفُونَ بِالْغَيْبِ مِن مَّكَانٍ بَعِيدٍ(53)

 Won kuku ti sai gbagbo ninu re siwaju (nile aye). Won si n soro nipa ikoko lati aye t’o jinna (iyen, ile aye)

وَحِيلَ بَيْنَهُمْ وَبَيْنَ مَا يَشْتَهُونَ كَمَا فُعِلَ بِأَشْيَاعِهِم مِّن قَبْلُ ۚ إِنَّهُمْ كَانُوا فِي شَكٍّ مُّرِيبٍ(54)

 A si fi gaga si aarin awon ati ohun ti won n soju kokoro re gege bi A ti se fun awon egbe won ni isaaju. Dajudaju won wa ninu iyemeji t’o gbopon (nipa Ojo Ajinde)


More surahs in Yoruba:


Al-Baqarah Al-'Imran An-Nisa'
Al-Ma'idah Yusuf Ibrahim
Al-Hijr Al-Kahf Maryam
Al-Hajj Al-Qasas Al-'Ankabut
As-Sajdah Ya Sin Ad-Dukhan
Al-Fath Al-Hujurat Qaf
An-Najm Ar-Rahman Al-Waqi'ah
Al-Hashr Al-Mulk Al-Haqqah
Al-Inshiqaq Al-A'la Al-Ghashiyah

Download surah Saba with the voice of the most famous Quran reciters :

surah Saba mp3 : choose the reciter to listen and download the chapter Saba Complete with high quality
surah Saba Ahmed El Agamy
Ahmed Al Ajmy
surah Saba Bandar Balila
Bandar Balila
surah Saba Khalid Al Jalil
Khalid Al Jalil
surah Saba Saad Al Ghamdi
Saad Al Ghamdi
surah Saba Saud Al Shuraim
Saud Al Shuraim
surah Saba Abdul Basit Abdul Samad
Abdul Basit
surah Saba Abdul Rashid Sufi
Abdul Rashid Sufi
surah Saba Abdullah Basfar
Abdullah Basfar
surah Saba Abdullah Awwad Al Juhani
Abdullah Al Juhani
surah Saba Fares Abbad
Fares Abbad
surah Saba Maher Al Muaiqly
Maher Al Muaiqly
surah Saba Muhammad Siddiq Al Minshawi
Al Minshawi
surah Saba Al Hosary
Al Hosary
surah Saba Al-afasi
Mishari Al-afasi
surah Saba Yasser Al Dosari
Yasser Al Dosari


Saturday, May 4, 2024

لا تنسنا من دعوة صالحة بظهر الغيب