سورة مريم باليوربا

  1. استمع للسورة
  2. سور أخرى
  3. ترجمة السورة
القرآن الكريم | ترجمة معاني القرآن | اللغة اليوربا | سورة مريم | Maryam - عدد آياتها 98 - رقم السورة في المصحف: 19 - معنى السورة بالإنجليزية: Mary.

كهيعص(1)

Kaf ha ya ‘aen sod. iya ‘Isa (’alaehi-ssolatu wa-ssalam) Oun l’O sa a lesa. Tohun ti bee naa iba ti so awon ododo wonyen nipa Moryam iya Jesu. Sebi won kuku fi enu abuku kan Moryam eda ni awon miiran ti Allahu fi sori awon surah oro Re. A kuku ri surah Muhammad gege bi a se ri surah Moryam. Amo iya ‘Isa so surah l’o maa so ‘Isa tabi iya re di oluwa ati olugbala? Tabi se nitori pe won fi oruko Moryam iya ‘Isa so surah l’o so ‘Isa tabi iya re di olohun omo? Tabi se nitori pe won fi oruko Moryam sise ti Allahu (subhanahu wa ta’ala) se Moryam ni esa eniyan amo ti Allahu ko se iya ati baba Anabi wa bee ti Allahu fi sori ebi Moryam a kuku ri surah Ƙuraes

ذِكْرُ رَحْمَتِ رَبِّكَ عَبْدَهُ زَكَرِيَّا(2)

(Eyi ni) iranti nipa ike ti Oluwa Re se fun erusin Re, (Anabi) Zakariyya

إِذْ نَادَىٰ رَبَّهُ نِدَاءً خَفِيًّا(3)

(Ranti) nigba ti o pe Oluwa re ni ipe ikoko

قَالَ رَبِّ إِنِّي وَهَنَ الْعَظْمُ مِنِّي وَاشْتَعَلَ الرَّأْسُ شَيْبًا وَلَمْ أَكُن بِدُعَائِكَ رَبِّ شَقِيًّا(4)

O so pe: "Oluwa mi, dajudaju eegun ara mi ti le, ori (mi) ti kun fun ewu, emi ko si nii pasan nipa bi mo se n pe O, Oluwa mi

وَإِنِّي خِفْتُ الْمَوَالِيَ مِن وَرَائِي وَكَانَتِ امْرَأَتِي عَاقِرًا فَهَبْ لِي مِن لَّدُنكَ وَلِيًّا(5)

Ati pe dajudaju mo n paya awon ibatan mi leyin (iku) mi. Iyawo mi si je agan. Nitori naa, ta mi lore lati odo Re omo rere kan

يَرِثُنِي وَيَرِثُ مِنْ آلِ يَعْقُوبَ ۖ وَاجْعَلْهُ رَبِّ رَضِيًّا(6)

(ti) o maa jogun mi, ti o si maa jogun awon ebi (Anabi) Ya‘ƙub. Ki O si se e ni eni ti O yonu si, Oluwa mi

يَا زَكَرِيَّا إِنَّا نُبَشِّرُكَ بِغُلَامٍ اسْمُهُ يَحْيَىٰ لَمْ نَجْعَل لَّهُ مِن قَبْلُ سَمِيًّا(7)

Zakariyya, dajudaju Awa maa fun o ni iro idunnu (nipa bibi) omokunrin kan, oruko re ni Yahya. A o fun eni kan ni (iru) oruko (yii) ri siwaju (re)

قَالَ رَبِّ أَنَّىٰ يَكُونُ لِي غُلَامٌ وَكَانَتِ امْرَأَتِي عَاقِرًا وَقَدْ بَلَغْتُ مِنَ الْكِبَرِ عِتِيًّا(8)

O so pe: "Oluwa mi, bawo ni mo se maa ni omo nigba ti iyawo mi je agan, ti mo si ti di agbalagba gan-an

قَالَ كَذَٰلِكَ قَالَ رَبُّكَ هُوَ عَلَيَّ هَيِّنٌ وَقَدْ خَلَقْتُكَ مِن قَبْلُ وَلَمْ تَكُ شَيْئًا(9)

(Molaika) so pe: “Bayen ni (o maa ri).” Oluwa re so pe: “O rorun fun Mi. Mo kuku da iwo naa siwaju (re), nigba ti iwo ko ti i je nnkan kan.”

قَالَ رَبِّ اجْعَل لِّي آيَةً ۚ قَالَ آيَتُكَ أَلَّا تُكَلِّمَ النَّاسَ ثَلَاثَ لَيَالٍ سَوِيًّا(10)

(Zakariyya) so pe: “Oluwa mi, fun mi ni ami kan.” (Molaika) so pe: "Ami re ni pe, o o nii le ba eniyan soro fun ojo meta, ki i se ti amodi

فَخَرَجَ عَلَىٰ قَوْمِهِ مِنَ الْمِحْرَابِ فَأَوْحَىٰ إِلَيْهِمْ أَن سَبِّحُوا بُكْرَةً وَعَشِيًّا(11)

Nigba naa, o jade si awon eniyan re lati inu ile ijosin. O si toka si won pe ki won maa se afomo (fun Allahu) ni owuro ati ni asale

يَا يَحْيَىٰ خُذِ الْكِتَابَ بِقُوَّةٍ ۖ وَآتَيْنَاهُ الْحُكْمَ صَبِيًّا(12)

Yahya, mu Tira naa dani daradara. A si fun un ni agboye esin lati kekere

وَحَنَانًا مِّن لَّدُنَّا وَزَكَاةً ۖ وَكَانَ تَقِيًّا(13)

(Anabi Yahya je) ike ati eni mimo kan lati odo Wa. O si je oluberu (Allahu)

وَبَرًّا بِوَالِدَيْهِ وَلَمْ يَكُن جَبَّارًا عَصِيًّا(14)

(O tun je) oniwa rere si awon obi re mejeeji. Ko si je ajeninipa, oluyapa

وَسَلَامٌ عَلَيْهِ يَوْمَ وُلِدَ وَيَوْمَ يَمُوتُ وَيَوْمَ يُبْعَثُ حَيًّا(15)

Alaafia ni fun un ni ojo ti won bi i, ati ni ojo ti o maa ku ati ni ojo ti A oo gbe e dide laaye (ni Ojo Ajinde)

وَاذْكُرْ فِي الْكِتَابِ مَرْيَمَ إِذِ انتَبَذَتْ مِنْ أَهْلِهَا مَكَانًا شَرْقِيًّا(16)

So itan Moryam ti o wa ninu al-Ƙur’an. (Ranti) nigba ti o yera kuro lodo awon eniyan re si aye kan ni ila oorun

فَاتَّخَذَتْ مِن دُونِهِمْ حِجَابًا فَأَرْسَلْنَا إِلَيْهَا رُوحَنَا فَتَمَثَّلَ لَهَا بَشَرًا سَوِيًّا(17)

O mu gaga kan (lati fi ara re pamo) fun won. A si ran molaika Wa si i. O si fara han an ni aworan abara pipe

قَالَتْ إِنِّي أَعُوذُ بِالرَّحْمَٰنِ مِنكَ إِن كُنتَ تَقِيًّا(18)

(Moryam) so pe: “Emi sa di Ajoke-aye kuro lodo re, ti o ba je oluberu (Allahu).”

قَالَ إِنَّمَا أَنَا رَسُولُ رَبِّكِ لِأَهَبَ لَكِ غُلَامًا زَكِيًّا(19)

(Molaika) so pe: “Emi ni Ojise Oluwa re, (O ran mi si o) pe ki ng fun o ni omokunrin mimo kan.”

قَالَتْ أَنَّىٰ يَكُونُ لِي غُلَامٌ وَلَمْ يَمْسَسْنِي بَشَرٌ وَلَمْ أَكُ بَغِيًّا(20)

O so pe: "Bawo ni mo se maa ni omo nigba ti abara kan ko fowo kan mi, ti emi ko si je alagbere

قَالَ كَذَٰلِكِ قَالَ رَبُّكِ هُوَ عَلَيَّ هَيِّنٌ ۖ وَلِنَجْعَلَهُ آيَةً لِّلنَّاسِ وَرَحْمَةً مِّنَّا ۚ وَكَانَ أَمْرًا مَّقْضِيًّا(21)

(Molaika) so pe: “Bayen l’o maa ri.” Oluwa re so pe: “O rorun fun mi. Ati pe nitori ki A le se e ni ami fun awon eniyan ni. O si je ike lati odo Wa. O tun je oro ti A ti pari.”

۞ فَحَمَلَتْهُ فَانتَبَذَتْ بِهِ مَكَانًا قَصِيًّا(22)

Nitori naa, o loyun re. O si yera pelu re si aye kan t’o jinna

فَأَجَاءَهَا الْمَخَاضُ إِلَىٰ جِذْعِ النَّخْلَةِ قَالَتْ يَا لَيْتَنِي مِتُّ قَبْلَ هَٰذَا وَكُنتُ نَسْيًا مَّنسِيًّا(23)

Irobi omo si mu un wa si idi igi dabinu. O so pe: “Haa! Ki ng ti ku siwaju eyi, ki ng si ti di eni ti won ti gbagbe patapata.”

فَنَادَاهَا مِن تَحْتِهَا أَلَّا تَحْزَنِي قَدْ جَعَلَ رَبُّكِ تَحْتَكِ سَرِيًّا(24)

Nigba naa, (molaika) pe e lati isale odo re pe: "Ma se banuje. Dajudaju Oluwa re ti se odo kekere kan si isale odo re

وَهُزِّي إِلَيْكِ بِجِذْعِ النَّخْلَةِ تُسَاقِطْ عَلَيْكِ رُطَبًا جَنِيًّا(25)

Mi igi dabinu naa sodo re, ki dabinu tutu, to to ka je si maa jabo sile fun o

فَكُلِي وَاشْرَبِي وَقَرِّي عَيْنًا ۖ فَإِمَّا تَرَيِنَّ مِنَ الْبَشَرِ أَحَدًا فَقُولِي إِنِّي نَذَرْتُ لِلرَّحْمَٰنِ صَوْمًا فَلَنْ أُكَلِّمَ الْيَوْمَ إِنسِيًّا(26)

Nitori naa, je, mu ki oju re si tutu. Ti o ba si ri eni kan ninu abara, so fun un pe: "Dajudaju mo jejee ikenuro fun Ajoke-aye. Nitori naa, mi o nii ba eniyan kan soro ni oni

فَأَتَتْ بِهِ قَوْمَهَا تَحْمِلُهُ ۖ قَالُوا يَا مَرْيَمُ لَقَدْ جِئْتِ شَيْئًا فَرِيًّا(27)

O si mu omo naa wa ba awon eniyan re (ni eni ti) o gbe e dani. Won so pe: "Moryam, dajudaju o ti gbe nnkan aburu nla wa

يَا أُخْتَ هَارُونَ مَا كَانَ أَبُوكِ امْرَأَ سَوْءٍ وَمَا كَانَتْ أُمُّكِ بَغِيًّا(28)

Arabinrin Harun, baba re ki i se eniyan buruku. Ati pe iya re ki i se alagbere

فَأَشَارَتْ إِلَيْهِ ۖ قَالُوا كَيْفَ نُكَلِّمُ مَن كَانَ فِي الْمَهْدِ صَبِيًّا(29)

O si toka si omo naa. Won so pe: “Bawo ni a o se ba eni t’o wa lori ite, t’o je omo oponlo soro?”

قَالَ إِنِّي عَبْدُ اللَّهِ آتَانِيَ الْكِتَابَ وَجَعَلَنِي نَبِيًّا(30)

(Omo naa) soro pe: "Dajudaju eru Allahu ni emi. (Allahu) fun mi ni Tira. O si se mi ni Anabi. eda ti o n bowo fun ilana ati ofin Olohun eda ti o juwo juse sile fun ilana ati ofin Olohun ati eda ti o n josin fun Olohun labe ilana ati ofin Olohun. Eda naa ko si nii yonu si ilana ati ofin miiran t’o yato si ti Olohun.” Eni ti o ba n se iwonyen fun ohun miiran tabi elomiiran but with my flesh I am a slave to the law of sin.” Itumo: “Nitori naa nigba naa pelu emi mi pelu okan ati ara wa ni a fi gba lati wa labe ofin Re. Iwonba asise ti a ba si fi ara se gege bi adamo eniyan ironupiwada ati itoro aforijin ni odo Allahu ni ona abayo lori re. Alaforijin

وَجَعَلَنِي مُبَارَكًا أَيْنَ مَا كُنتُ وَأَوْصَانِي بِالصَّلَاةِ وَالزَّكَاةِ مَا دُمْتُ حَيًّا(31)

O se mi ni eni ibukun ni ibikibi ti mo ba wa. O pa mi lase irun kiki ati Zakah yiyo lodiwon igba ti mo ba wa nipo alaaye (lori ile aye)

وَبَرًّا بِوَالِدَتِي وَلَمْ يَجْعَلْنِي جَبَّارًا شَقِيًّا(32)

(O se mi ni) oniwa rere si iya mi. Ko si se mi ni ajeninipa, olori buruku

وَالسَّلَامُ عَلَيَّ يَوْمَ وُلِدتُّ وَيَوْمَ أَمُوتُ وَيَوْمَ أُبْعَثُ حَيًّا(33)

Alaafia ni fun mi ni ojo ti won bi mi, ati ni ojo ti mo maa ku ati ni ojo ti Won a gbe mi dide ni alaaye (ni Ojo Ajinde)

ذَٰلِكَ عِيسَى ابْنُ مَرْيَمَ ۚ قَوْلَ الْحَقِّ الَّذِي فِيهِ يَمْتَرُونَ(34)

Iyen ni (Anabi) ‘Isa omo Moryam. (Eyi je) oro ododo ti awon (yehudi ati nasara) n seyemeji nipa re

مَا كَانَ لِلَّهِ أَن يَتَّخِذَ مِن وَلَدٍ ۖ سُبْحَانَهُ ۚ إِذَا قَضَىٰ أَمْرًا فَإِنَّمَا يَقُولُ لَهُ كُن فَيَكُونُ(35)

Ko ye fun Allahu lati so eni kan kan di omo. Mimo ni fun Un. Nigba ti O ba pebubu kini kan, O kan maa so fun un pe: "Je bee." O si maa je bee

وَإِنَّ اللَّهَ رَبِّي وَرَبُّكُمْ فَاعْبُدُوهُ ۚ هَٰذَا صِرَاطٌ مُّسْتَقِيمٌ(36)

Ati pe dajudaju Allahu ni Oluwa mi ati Oluwa yin. Nitori naa, e josin fun Un. Eyi ni ona taara

فَاخْتَلَفَ الْأَحْزَابُ مِن بَيْنِهِمْ ۖ فَوَيْلٌ لِّلَّذِينَ كَفَرُوا مِن مَّشْهَدِ يَوْمٍ عَظِيمٍ(37)

Awon ijo (yehudi ati nasara) si yapa enu (si eyi) laaarin ara won. Nitori naa, egbe ni fun awon t’o sai gbagbo (ni asiko) ijerii gbangba lojo nla (Ojo Ajinde)

أَسْمِعْ بِهِمْ وَأَبْصِرْ يَوْمَ يَأْتُونَنَا ۖ لَٰكِنِ الظَّالِمُونَ الْيَوْمَ فِي ضَلَالٍ مُّبِينٍ(38)

Ki ni won ko nii gbo, ki si ni won ko nii ri ni ojo ti won yoo wa ba Wa! Sugbon awon alabosi ni ojo naa ti wa ninu isina ponnbele

وَأَنذِرْهُمْ يَوْمَ الْحَسْرَةِ إِذْ قُضِيَ الْأَمْرُ وَهُمْ فِي غَفْلَةٍ وَهُمْ لَا يُؤْمِنُونَ(39)

Sekilo ojo abamo fun won nigba ti A ba pari oro, (pe ko nii si iku mo, amo) won wa ninu igbagbera bayii na, won ko si gbagbo

إِنَّا نَحْنُ نَرِثُ الْأَرْضَ وَمَنْ عَلَيْهَا وَإِلَيْنَا يُرْجَعُونَ(40)

Dajudaju Awa l’A maa jogun ile ati awon t’o n be lori re. Odo Wa si ni won yoo da yin pada si

وَاذْكُرْ فِي الْكِتَابِ إِبْرَاهِيمَ ۚ إِنَّهُ كَانَ صِدِّيقًا نَّبِيًّا(41)

Mu (itan) ’Ibrohim wa si iranti (bi o se) wa ninu al-Ƙur’an. Dajudaju o je olododo ponnbele, (o si je) Anabi

إِذْ قَالَ لِأَبِيهِ يَا أَبَتِ لِمَ تَعْبُدُ مَا لَا يَسْمَعُ وَلَا يُبْصِرُ وَلَا يُغْنِي عَنكَ شَيْئًا(42)

Ranti nigba ti o so fun baba re pe: "Baba mi, nitori ki ni o fi n josin fun ohun ti ko gboro, ti ko riran, ti ko si le ro o loro kan kan

يَا أَبَتِ إِنِّي قَدْ جَاءَنِي مِنَ الْعِلْمِ مَا لَمْ يَأْتِكَ فَاتَّبِعْنِي أَهْدِكَ صِرَاطًا سَوِيًّا(43)

Baba mi, dajudaju imo ti iwo ko ni ti de ba mi. Nitori naa, tele mi, ki ng fi ona taara mo o

يَا أَبَتِ لَا تَعْبُدِ الشَّيْطَانَ ۖ إِنَّ الشَّيْطَانَ كَانَ لِلرَّحْمَٰنِ عَصِيًّا(44)

Baba mi, ma se bo Esu. Dajudaju Esu je oluyapa ase Ajoke-aye

يَا أَبَتِ إِنِّي أَخَافُ أَن يَمَسَّكَ عَذَابٌ مِّنَ الرَّحْمَٰنِ فَتَكُونَ لِلشَّيْطَانِ وَلِيًّا(45)

Baba mi, dajudaju emi n paya pe ki iya kan lati odo Ajoke-aye ma fowo ba o nitori ki iwo ma baa di ore Esu (ninu Ina)

قَالَ أَرَاغِبٌ أَنتَ عَنْ آلِهَتِي يَا إِبْرَاهِيمُ ۖ لَئِن لَّمْ تَنتَهِ لَأَرْجُمَنَّكَ ۖ وَاهْجُرْنِي مَلِيًّا(46)

(Baba re) wi pe: “Se iwo yoo ko awon olohun mi sile ni, ’Ibrohim? Dajudaju ti o o ba jawo (ninu ohun ti o n so), dajudaju mo maa le o loko pa. Tie yera fun mi woorowo na.”

قَالَ سَلَامٌ عَلَيْكَ ۖ سَأَسْتَغْفِرُ لَكَ رَبِّي ۖ إِنَّهُ كَانَ بِي حَفِيًّا(47)

(’Ibrohim) so pe: "Alaafia ki o maa ba o. Mo maa ba o toro aforijin lodo Oluwa mi. Dajudaju O je Oloore mi

وَأَعْتَزِلُكُمْ وَمَا تَدْعُونَ مِن دُونِ اللَّهِ وَأَدْعُو رَبِّي عَسَىٰ أَلَّا أَكُونَ بِدُعَاءِ رَبِّي شَقِيًّا(48)

Ati pe mo maa yera fun eyin ati nnkan ti e n josin fun leyin Allahu. Emi yo si maa pe Oluwa mi. O si sunmo pe emi ko nii pasan pelu adua mi si Oluwa mi

فَلَمَّا اعْتَزَلَهُمْ وَمَا يَعْبُدُونَ مِن دُونِ اللَّهِ وَهَبْنَا لَهُ إِسْحَاقَ وَيَعْقُوبَ ۖ وَكُلًّا جَعَلْنَا نَبِيًّا(49)

Nigba ti o yera fun awon ati nnkan ti won n josin fun leyin Allahu, A si ta a lore (omo), ’Ishaƙ ati Ya‘ƙub (omoomo). A si se okookan won ni Anabi

وَوَهَبْنَا لَهُم مِّن رَّحْمَتِنَا وَجَعَلْنَا لَهُمْ لِسَانَ صِدْقٍ عَلِيًّا(50)

Ati pe A ta won lore lati inu ike Wa. A si ni ki won maa soro won ni daadaa

وَاذْكُرْ فِي الْكِتَابِ مُوسَىٰ ۚ إِنَّهُ كَانَ مُخْلَصًا وَكَانَ رَسُولًا نَّبِيًّا(51)

So itan (Anabi) Musa ti o wa ninu al-Ƙur’an. Dajudaju o je eni-esa, o je Ojise, (o tun je) Anabi

وَنَادَيْنَاهُ مِن جَانِبِ الطُّورِ الْأَيْمَنِ وَقَرَّبْنَاهُ نَجِيًّا(52)

A pe e ni eba apata ni apa owo otun (Musa). A si mu un sunmo tosi lati ba a soro

وَوَهَبْنَا لَهُ مِن رَّحْمَتِنَا أَخَاهُ هَارُونَ نَبِيًّا(53)

Lati inu ike Wa A si fi arakunrin re, Harun, (ti o je) Anabi, ta a lore

وَاذْكُرْ فِي الْكِتَابِ إِسْمَاعِيلَ ۚ إِنَّهُ كَانَ صَادِقَ الْوَعْدِ وَكَانَ رَسُولًا نَّبِيًّا(54)

So itan (Anabi) ’Ismo‘il ti o wa ninu al-Ƙur’an. Dajudaju o je olumu-adehun-se, o je Ojise, (o tun je) Anabi

وَكَانَ يَأْمُرُ أَهْلَهُ بِالصَّلَاةِ وَالزَّكَاةِ وَكَانَ عِندَ رَبِّهِ مَرْضِيًّا(55)

O maa n pa ara ile re ni ase irun kiki ati Zakah yiyo. O si je eni iyonu lodo Oluwa re

وَاذْكُرْ فِي الْكِتَابِ إِدْرِيسَ ۚ إِنَّهُ كَانَ صِدِّيقًا نَّبِيًّا(56)

So itan (Anabi) ’Idris ti o wa ninu al-Ƙur’an. Dajudaju o je olododo ponnbele, (o si je) Anabi

وَرَفَعْنَاهُ مَكَانًا عَلِيًّا(57)

A si gbe e si aye giga (ninu sanmo)

أُولَٰئِكَ الَّذِينَ أَنْعَمَ اللَّهُ عَلَيْهِم مِّنَ النَّبِيِّينَ مِن ذُرِّيَّةِ آدَمَ وَمِمَّنْ حَمَلْنَا مَعَ نُوحٍ وَمِن ذُرِّيَّةِ إِبْرَاهِيمَ وَإِسْرَائِيلَ وَمِمَّنْ هَدَيْنَا وَاجْتَبَيْنَا ۚ إِذَا تُتْلَىٰ عَلَيْهِمْ آيَاتُ الرَّحْمَٰنِ خَرُّوا سُجَّدًا وَبُكِيًّا ۩(58)

Awon wonyen ni awon ti Allahu se idera fun ninu awon Anabi, ninu awon aromodomo (Anabi) Adam ati ninu awon ti A gbe gun oko oju-omi pelu (Anabi) Nuh ati ninu aromodomo (Anabi) ’Ibrohim ati ’Isro’il ati ninu awon ti A ti fi mona, ti A si sa lesa. Nigba ti won ba n ke awon ayah Ajoke-aye fun won, won maa doju bole; ti won a forikanle, ti won a si maa sunkun

۞ فَخَلَفَ مِن بَعْدِهِمْ خَلْفٌ أَضَاعُوا الصَّلَاةَ وَاتَّبَعُوا الشَّهَوَاتِ ۖ فَسَوْفَ يَلْقَوْنَ غَيًّا(59)

Awon arole kan si role leyin won, ti won ra irun kiki lare, ti won tele awon yodoyindin emi. Laipe won maa pade iparun (ninu Ina)

إِلَّا مَن تَابَ وَآمَنَ وَعَمِلَ صَالِحًا فَأُولَٰئِكَ يَدْخُلُونَ الْجَنَّةَ وَلَا يُظْلَمُونَ شَيْئًا(60)

Ayafi eni ti o ba ronu piwada, ti o gbagbo ni ododo, ti o si se ise rere. Awon wonyen ni won yoo wo inu Ogba Idera. A o si nii sabosi kan kan si won

جَنَّاتِ عَدْنٍ الَّتِي وَعَدَ الرَّحْمَٰنُ عِبَادَهُ بِالْغَيْبِ ۚ إِنَّهُ كَانَ وَعْدُهُ مَأْتِيًّا(61)

(Won yoo wo inu) awon Ogba Idera gbere ti Ajoke-aye se ni adehun si ipamo fun awon erusin Re. Dajudaju (Allahu), adehun Re n bo wa se

لَّا يَسْمَعُونَ فِيهَا لَغْوًا إِلَّا سَلَامًا ۖ وَلَهُمْ رِزْقُهُمْ فِيهَا بُكْرَةً وَعَشِيًّا(62)

Won ko nii gbo isokuso ninu re afi alaafia. Ije-imu won wa ninu re ni owuro ati ni asale

تِلْكَ الْجَنَّةُ الَّتِي نُورِثُ مِنْ عِبَادِنَا مَن كَانَ تَقِيًّا(63)

Iyen ni Ogba Idera ti A oo jogun re fun eni ti o je oluberu (Mi) ninu awon erusin Wa

وَمَا نَتَنَزَّلُ إِلَّا بِأَمْرِ رَبِّكَ ۖ لَهُ مَا بَيْنَ أَيْدِينَا وَمَا خَلْفَنَا وَمَا بَيْنَ ذَٰلِكَ ۚ وَمَا كَانَ رَبُّكَ نَسِيًّا(64)

Awa (molaika) ki i sokale ayafi pelu ase Oluwa re. TiRe ni ohun ti n be niwaju wa, ohun ti n be ni eyin wa ati ohun ti n be laaarin (mejeeji) yii. Oluwa re ki i si se onigbagbe

رَّبُّ السَّمَاوَاتِ وَالْأَرْضِ وَمَا بَيْنَهُمَا فَاعْبُدْهُ وَاصْطَبِرْ لِعِبَادَتِهِ ۚ هَلْ تَعْلَمُ لَهُ سَمِيًّا(65)

Oluwa awon sanmo ati ile ati ohun ti n be laaarin awon mejeeji. Nitori naa, josin fun Un, ki o si se suuru lori ijosin Re. Nje o mo eni ti o tun n je oruko Re

وَيَقُولُ الْإِنسَانُ أَإِذَا مَا مِتُّ لَسَوْفَ أُخْرَجُ حَيًّا(66)

Eniyan n wi pe: “Se nigba ti mo ba ku, Won yoo tun mu mi jade laipe ni alaaye?”

أَوَلَا يَذْكُرُ الْإِنسَانُ أَنَّا خَلَقْنَاهُ مِن قَبْلُ وَلَمْ يَكُ شَيْئًا(67)

Se eniyan ko ranti pe dajudaju Awa ni A seda re teletele nigba ti ko ti i je nnkan kan

فَوَرَبِّكَ لَنَحْشُرَنَّهُمْ وَالشَّيَاطِينَ ثُمَّ لَنُحْضِرَنَّهُمْ حَوْلَ جَهَنَّمَ جِثِيًّا(68)

Nitori naa, mo fi Oluwa re bura; dajudaju A maa ko awon ati awon esu jo. Leyin naa, dajudaju A maa mu won wa si ayika ina Jahanamo lori ikunle

ثُمَّ لَنَنزِعَنَّ مِن كُلِّ شِيعَةٍ أَيُّهُمْ أَشَدُّ عَلَى الرَّحْمَٰنِ عِتِيًّا(69)

Leyin naa, dajudaju A maa mu jade ninu ijo kookan eyikeyii ninu won ti o le julo ni ese dida si Ajoke-aye

ثُمَّ لَنَحْنُ أَعْلَمُ بِالَّذِينَ هُمْ أَوْلَىٰ بِهَا صِلِيًّا(70)

Leyin naa, dajudaju Awa nimo julo nipa awon t’o letoo si wiwo inu Ina

وَإِن مِّنكُمْ إِلَّا وَارِدُهَا ۚ كَانَ عَلَىٰ رَبِّكَ حَتْمًا مَّقْضِيًّا(71)

Ko si eni kan ninu yin afi ki o debe. O je isele dandan lodo Oluwa re. 74:30-31. Bakan naa, kalmoh “warid” t’o jeyo ninu ayah 71 je oro-oruko ti won seda lati ara oro-ise “warada”. Ninu al-Ƙur’an, itumo meji pere l’o wa fun “warada”. “Warada” tumo si “o de si ibi ti kini kan wa, o si wo inu nnkan naa”, gege bi itumo yii se wa ninu surah Hud 11:98 ati surah al-’Anbiya’

ثُمَّ نُنَجِّي الَّذِينَ اتَّقَوا وَّنَذَرُ الظَّالِمِينَ فِيهَا جِثِيًّا(72)

igun kiini keji maa wa labe akorin awon molaika kan ni. Iyen ni pe awon molaika kan l’o maa ko gbogbo eda lo sori afara Ina nitori pe

وَإِذَا تُتْلَىٰ عَلَيْهِمْ آيَاتُنَا بَيِّنَاتٍ قَالَ الَّذِينَ كَفَرُوا لِلَّذِينَ آمَنُوا أَيُّ الْفَرِيقَيْنِ خَيْرٌ مَّقَامًا وَأَحْسَنُ نَدِيًّا(73)

Nigba ti won ba n ke awon ayah Wa t’o yanju fun won, awon t’o sai gbagbo yoo so fun awon t’o gbagbo ni ododo pe: “Ewo ninu ijo mejeeji (awa tabi eyin) l’o loore julo ni ibugbe, l’o si dara julo ni ijokoo?”

وَكَمْ أَهْلَكْنَا قَبْلَهُم مِّن قَرْنٍ هُمْ أَحْسَنُ أَثَاثًا وَرِئْيًا(74)

Ati pe meloo meloo ninu awon iran ti A ti pare siwaju won, ti won dara julo ni oro (aye) ati ni irisi

قُلْ مَن كَانَ فِي الضَّلَالَةِ فَلْيَمْدُدْ لَهُ الرَّحْمَٰنُ مَدًّا ۚ حَتَّىٰ إِذَا رَأَوْا مَا يُوعَدُونَ إِمَّا الْعَذَابَ وَإِمَّا السَّاعَةَ فَسَيَعْلَمُونَ مَنْ هُوَ شَرٌّ مَّكَانًا وَأَضْعَفُ جُندًا(75)

So pe: “Eni ti o ba wa ninu isina, Ajoke-aye yo si fe (isina) loju fun un taara, titi di igba ti won maa ri ohun ti won n se ni adehun fun won, yala iya tabi Akoko naa. Nigba naa, won yoo mo eni ti o buru julo ni ipo, ti o si le julo ni omo ogun

وَيَزِيدُ اللَّهُ الَّذِينَ اهْتَدَوْا هُدًى ۗ وَالْبَاقِيَاتُ الصَّالِحَاتُ خَيْرٌ عِندَ رَبِّكَ ثَوَابًا وَخَيْرٌ مَّرَدًّا(76)

Allahu yo si salekun imona fun awon t’o mona. Awon ise rere elesan gbere loore julo ni esan, o si loore julo ni ibudesi lodo Oluwa re

أَفَرَأَيْتَ الَّذِي كَفَرَ بِآيَاتِنَا وَقَالَ لَأُوتَيَنَّ مَالًا وَوَلَدًا(77)

So fun mi nipa eni t’o sai gbagbo ninu awon ayah Wa, ti o si wi pe: “Dajudaju won yoo fun mi ni dukia ati omo!”

أَطَّلَعَ الْغَيْبَ أَمِ اتَّخَذَ عِندَ الرَّحْمَٰنِ عَهْدًا(78)

Se o ri ikoko ni tabi o ri adehun kan gba lodo Ajoke-aye

كَلَّا ۚ سَنَكْتُبُ مَا يَقُولُ وَنَمُدُّ لَهُ مِنَ الْعَذَابِ مَدًّا(79)

Rara. A maa sakosile ohun t’o n wi. A si maa fe iya loju fun un taara

وَنَرِثُهُ مَا يَقُولُ وَيَأْتِينَا فَرْدًا(80)

A o si jogun ohun t’o n wi fun un. O si maa wa ba Wa ni oun nikan

وَاتَّخَذُوا مِن دُونِ اللَّهِ آلِهَةً لِّيَكُونُوا لَهُمْ عِزًّا(81)

Won so awon kan di olohun leyin Allahu nitori ki won le fun won ni agbara

كَلَّا ۚ سَيَكْفُرُونَ بِعِبَادَتِهِمْ وَيَكُونُونَ عَلَيْهِمْ ضِدًّا(82)

Rara. Won maa tako ijosin won, won si maa di ota won

أَلَمْ تَرَ أَنَّا أَرْسَلْنَا الشَّيَاطِينَ عَلَى الْكَافِرِينَ تَؤُزُّهُمْ أَزًّا(83)

Se o o ri i pe dajudaju Awa n ran awon esu si awon alaigbagbo ni, ti won si n ti won ni itikuti (sibi ese)

فَلَا تَعْجَلْ عَلَيْهِمْ ۖ إِنَّمَا نَعُدُّ لَهُمْ عَدًّا(84)

Nitori naa, ma se kanju nipa (iya) won. A kuku n ka (ojo) fun won ni kika taara

يَوْمَ نَحْشُرُ الْمُتَّقِينَ إِلَى الرَّحْمَٰنِ وَفْدًا(85)

(Ranti) ojo ti A oo ko awon oluberu (Allahu) jo sodo Ajoke-aye lori nnkan igun

وَنَسُوقُ الْمُجْرِمِينَ إِلَىٰ جَهَنَّمَ وِرْدًا(86)

A si maa da awon elese lo sinu ina Jahanamo witiwiti

لَّا يَمْلِكُونَ الشَّفَاعَةَ إِلَّا مَنِ اتَّخَذَ عِندَ الرَّحْمَٰنِ عَهْدًا(87)

Won ko nii ni ikapa isipe afi eni ti o ba gba adehun lati odo Ajoke-aye

وَقَالُوا اتَّخَذَ الرَّحْمَٰنُ وَلَدًا(88)

Won wi pe: "Ajoke-aye fi eni kan se omo

لَّقَدْ جِئْتُمْ شَيْئًا إِدًّا(89)

Dajudaju e ti mu nnkan aburu wa

تَكَادُ السَّمَاوَاتُ يَتَفَطَّرْنَ مِنْهُ وَتَنشَقُّ الْأَرْضُ وَتَخِرُّ الْجِبَالُ هَدًّا(90)

Awon sanmo fere faya perepere nitori re, ile fere faya perepere, awon apata si fere da wo lule gbi

أَن دَعَوْا لِلرَّحْمَٰنِ وَلَدًا(91)

fun wi pe won pe eni kan ni omo Ajoke-aye

وَمَا يَنبَغِي لِلرَّحْمَٰنِ أَن يَتَّخِذَ وَلَدًا(92)

Ko si ye fun Ajoke-aye lati fi eni kan se omo

إِن كُلُّ مَن فِي السَّمَاوَاتِ وَالْأَرْضِ إِلَّا آتِي الرَّحْمَٰنِ عَبْدًا(93)

Ko si eni kan ninu awon sanmo ati ile ayafi ki o wa ba Ajoke-aye ni ipo erusin

لَّقَدْ أَحْصَاهُمْ وَعَدَّهُمْ عَدًّا(94)

Dajudaju (Allahu) mo won. O si ka onka won taara

وَكُلُّهُمْ آتِيهِ يَوْمَ الْقِيَامَةِ فَرْدًا(95)

Gbogbo won yo si wa ba A ni Ojo Ajinde ni ikookan

إِنَّ الَّذِينَ آمَنُوا وَعَمِلُوا الصَّالِحَاتِ سَيَجْعَلُ لَهُمُ الرَّحْمَٰنُ وُدًّا(96)

Dajudaju awon t’o gbagbo ni ododo, ti won si se ise rere, Ajoke-aye yoo fi ife saaarin won

فَإِنَّمَا يَسَّرْنَاهُ بِلِسَانِكَ لِتُبَشِّرَ بِهِ الْمُتَّقِينَ وَتُنذِرَ بِهِ قَوْمًا لُّدًّا(97)

Nitori naa, A kuku se kike al-Ƙur’an ni irorun (fun o) pelu ede abinibi re nitori ki o le fi se iro idunnu fun awon oluberu (Allahu) ati nitori ki o le fi se ikilo fun ijo oniyan-jija

وَكَمْ أَهْلَكْنَا قَبْلَهُم مِّن قَرْنٍ هَلْ تُحِسُّ مِنْهُم مِّنْ أَحَدٍ أَوْ تَسْمَعُ لَهُمْ رِكْزًا(98)

Meloo meloo ninu iran ti A ti pare siwaju won! Nje o gbo iro eni kan kan ninu won mo tabi (nje) o gbo ohun kelekele kan lati odo won bi


المزيد من السور باللغة اليوربا:

سورة البقرة آل عمران سورة النساء
سورة المائدة سورة يوسف سورة ابراهيم
سورة الحجر سورة الكهف سورة مريم
سورة السجدة سورة يس سورة الدخان
سورة النجم سورة الرحمن سورة الواقعة
سورة الحشر سورة الملك سورة الحاقة

تحميل سورة مريم بصوت أشهر القراء :

قم باختيار القارئ للاستماع و تحميل سورة مريم كاملة بجودة عالية
سورة مريم أحمد العجمي
أحمد العجمي
سورة مريم خالد الجليل
خالد الجليل
سورة مريم سعد الغامدي
سعد الغامدي
سورة مريم سعود الشريم
سعود الشريم
سورة مريم عبد الباسط عبد الصمد
عبد الباسط
سورة مريم عبد الله عواد الجهني
عبد الله الجهني
سورة مريم علي الحذيفي
علي الحذيفي
سورة مريم فارس عباد
فارس عباد
سورة مريم ماهر المعيقلي
ماهر المعيقلي
سورة مريم محمد جبريل
محمد جبريل
سورة مريم محمد صديق المنشاوي
المنشاوي
سورة مريم الحصري
الحصري
سورة مريم العفاسي
مشاري العفاسي
سورة مريم ناصر القطامي
ناصر القطامي
سورة مريم ياسر الدوسري
ياسر الدوسري



Friday, May 3, 2024

لا تنسنا من دعوة صالحة بظهر الغيب