سورة الشعراء باليوربا

  1. استمع للسورة
  2. سور أخرى
  3. ترجمة السورة
القرآن الكريم | ترجمة معاني القرآن | اللغة اليوربا | سورة الشعراء | Shuara - عدد آياتها 227 - رقم السورة في المصحف: 26 - معنى السورة بالإنجليزية: The Poets.

طسم(1)

To sin mim

تِلْكَ آيَاتُ الْكِتَابِ الْمُبِينِ(2)

Iwonyi ni awon ayah Tira t’o n yanju oro eda

لَعَلَّكَ بَاخِعٌ نَّفْسَكَ أَلَّا يَكُونُوا مُؤْمِنِينَ(3)

Nitori ki ni o se maa para re pe won ko je onigbagbo ododo

إِن نَّشَأْ نُنَزِّلْ عَلَيْهِم مِّنَ السَّمَاءِ آيَةً فَظَلَّتْ أَعْنَاقُهُمْ لَهَا خَاضِعِينَ(4)

Ti A ba fe, A maa so ami kan kale fun won lati sanmo. Awon orun won ko si nii ye teriba fun un

وَمَا يَأْتِيهِم مِّن ذِكْرٍ مِّنَ الرَّحْمَٰنِ مُحْدَثٍ إِلَّا كَانُوا عَنْهُ مُعْرِضِينَ(5)

Ko si iranti kan ti o maa de ba won ni titun lati odo Ajoke-aye afi ki won je olugbunri kuro nibe

فَقَدْ كَذَّبُوا فَسَيَأْتِيهِمْ أَنبَاءُ مَا كَانُوا بِهِ يَسْتَهْزِئُونَ(6)

Dajudaju won ti pe (ayah Wa) niro. Nitori naa, awon iro ohun ti won n fi se yeye n bo wa ba won

أَوَلَمْ يَرَوْا إِلَى الْأَرْضِ كَمْ أَنبَتْنَا فِيهَا مِن كُلِّ زَوْجٍ كَرِيمٍ(7)

Se won ko ri ile pe meloo meloo ninu gbogbo orisirisi nnkan alapon-onle ti A mu hu jade lati inu re

إِنَّ فِي ذَٰلِكَ لَآيَةً ۖ وَمَا كَانَ أَكْثَرُهُم مُّؤْمِنِينَ(8)

Dajudaju ami wa ninu iyen. Sibesibe opolopo won ko je onigbagbo ododo

وَإِنَّ رَبَّكَ لَهُوَ الْعَزِيزُ الرَّحِيمُ(9)

Dajudaju Oluwa re, Oun ma ni Alagbara, Asake-orun

وَإِذْ نَادَىٰ رَبُّكَ مُوسَىٰ أَنِ ائْتِ الْقَوْمَ الظَّالِمِينَ(10)

(Ranti) nigba ti Oluwa re pe (Anabi) Musa pe: "Lo ba ijo alabosi

قَوْمَ فِرْعَوْنَ ۚ أَلَا يَتَّقُونَ(11)

ijo Fir‘aon (ki o si so fun won) pe Se won ko nii beru (Allahu) ni

قَالَ رَبِّ إِنِّي أَخَافُ أَن يُكَذِّبُونِ(12)

O so pe: "Oluwa mi, dajudaju emi n beru pe won maa pe mi ni opuro

وَيَضِيقُ صَدْرِي وَلَا يَنطَلِقُ لِسَانِي فَأَرْسِلْ إِلَىٰ هَارُونَ(13)

O si maa je inira fun mi (ti won ba pe mi ni opuro). Ahon mi ko si ja gaaraga. Nitori naa, ranse si Harun

وَلَهُمْ عَلَيَّ ذَنبٌ فَأَخَافُ أَن يَقْتُلُونِ(14)

Ati pe mo ni ese kan lorun lodo won. Nitori naa, mo n beru pe won maa pa mi

قَالَ كَلَّا ۖ فَاذْهَبَا بِآيَاتِنَا ۖ إِنَّا مَعَكُم مُّسْتَمِعُونَ(15)

(Allahu) so pe: "Rara (won ko le pa o). Nitori naa, ki eyin mejeeji mu awon ami (ise iyanu) Wa lo (ba won). Dajudaju Awa n be pelu yin; A n gbo (oro yin)

فَأْتِيَا فِرْعَوْنَ فَقُولَا إِنَّا رَسُولُ رَبِّ الْعَالَمِينَ(16)

Eyin mejeeji, e lo ba Fir‘aon. Ki e so fun un pe: Dajudaju awa ni Ojise Oluwa gbogbo eda

أَنْ أَرْسِلْ مَعَنَا بَنِي إِسْرَائِيلَ(17)

(A n so fun o) pe ki o je ki awon omo ’Isro’il maa ba wa lo

قَالَ أَلَمْ نُرَبِّكَ فِينَا وَلِيدًا وَلَبِثْتَ فِينَا مِنْ عُمُرِكَ سِنِينَ(18)

(Fir‘aon) wi pe: “Se ki i se ni aarin wa ni a ti to o ni kekere ni, ti o si gbe ni odo wa fun odun pupo ninu isemi aye re

وَفَعَلْتَ فَعْلَتَكَ الَّتِي فَعَلْتَ وَأَنتَ مِنَ الْكَافِرِينَ(19)

O si se ise owo re ti o se (si wa). Iwo si wa ninu awon alaimoore.”

قَالَ فَعَلْتُهَا إِذًا وَأَنَا مِنَ الضَّالِّينَ(20)

(Anabi Musa) so pe: "Mo se e nigba naa nigba ti mo wa ninu awon alaimokan ni

فَفَرَرْتُ مِنكُمْ لَمَّا خِفْتُكُمْ فَوَهَبَ لِي رَبِّي حُكْمًا وَجَعَلَنِي مِنَ الْمُرْسَلِينَ(21)

Mo si sa fun yin nigba ti mo beru yin. Nitori naa, Allahu ti ta mi lore ipo Anabi. O si se mi ni (okan) ninu awon Ojise

وَتِلْكَ نِعْمَةٌ تَمُنُّهَا عَلَيَّ أَنْ عَبَّدتَّ بَنِي إِسْرَائِيلَ(22)

Ati pe iyen ni idera ti o n se iregun re le mi lori. Pe o so awon omo ’Isro’il di eru (nko)

قَالَ فِرْعَوْنُ وَمَا رَبُّ الْعَالَمِينَ(23)

Fir‘aon wi pe: “Ki ni Oluwa gbogbo eda?”

قَالَ رَبُّ السَّمَاوَاتِ وَالْأَرْضِ وَمَا بَيْنَهُمَا ۖ إِن كُنتُم مُّوقِنِينَ(24)

(Anabi Musa) so pe: “(Allahu ni)

قَالَ لِمَنْ حَوْلَهُ أَلَا تَسْتَمِعُونَ(25)

(Fir‘aon) wi fun awon t’o wa ni ayika re pe: “Se e e gbo oro (t’o n so ni)?”

قَالَ رَبُّكُمْ وَرَبُّ آبَائِكُمُ الْأَوَّلِينَ(26)

(Anabi Musa) so pe: “(Allahu ni) Oluwa yin ati Oluwa awon baba yin, awon eni akoko.”

قَالَ إِنَّ رَسُولَكُمُ الَّذِي أُرْسِلَ إِلَيْكُمْ لَمَجْنُونٌ(27)

(Fir‘aon) wi pe: “Dajudaju Ojise yin eyi ti won ran si yin, were ma ni.”

قَالَ رَبُّ الْمَشْرِقِ وَالْمَغْرِبِ وَمَا بَيْنَهُمَا ۖ إِن كُنتُمْ تَعْقِلُونَ(28)

(Anabi Musa) so pe: “(Allahu ni) Oluwa ibuyo oorun, ibuwo oorun ati ohunkohun t’o n be laaarin awon mejeeji, ti e ba maa n se laakaye.”

قَالَ لَئِنِ اتَّخَذْتَ إِلَٰهًا غَيْرِي لَأَجْعَلَنَّكَ مِنَ الْمَسْجُونِينَ(29)

(Fir‘aon) wi pe: “Dajudaju ti o ba fi le josin fun olohun kan yato si mi, dajudaju mo maa so o di ara awon elewon.”

قَالَ أَوَلَوْ جِئْتُكَ بِشَيْءٍ مُّبِينٍ(30)

(Anabi Musa) so pe: “Ti o ba je pe mo mu kini kan t’o yanju wa fun o nko?”

قَالَ فَأْتِ بِهِ إِن كُنتَ مِنَ الصَّادِقِينَ(31)

(Fir‘aon) wi pe: “Mu un wa nigba naa ti iwo ba wa ninu awon olododo.”

فَأَلْقَىٰ عَصَاهُ فَإِذَا هِيَ ثُعْبَانٌ مُّبِينٌ(32)

Nitori naa, o ju opa re sile, o si di ejo ponnbele

وَنَزَعَ يَدَهُ فَإِذَا هِيَ بَيْضَاءُ لِلنَّاظِرِينَ(33)

O tun fa owo re yo sita, o si di funfun fun awon oluworan

قَالَ لِلْمَلَإِ حَوْلَهُ إِنَّ هَٰذَا لَسَاحِرٌ عَلِيمٌ(34)

(Fir‘aon) wi fun awon ijoye ti won wa ni ayika re pe: “Dajudaju eyi ni onimo nipa idan pipa

يُرِيدُ أَن يُخْرِجَكُم مِّنْ أَرْضِكُم بِسِحْرِهِ فَمَاذَا تَأْمُرُونَ(35)

O fe ko yin kuro lori ile yin ni. Ki ni ohun ti e maa mu wa ni imoran?”

قَالُوا أَرْجِهْ وَأَخَاهُ وَابْعَثْ فِي الْمَدَائِنِ حَاشِرِينَ(36)

Won wi pe: "Da oun ati arakunrin re duro na, ki o si ran awon akonijo si awon ilu

يَأْتُوكَ بِكُلِّ سَحَّارٍ عَلِيمٍ(37)

(pe) ki gbogbo onimo nipa idan pipa wa ba o

فَجُمِعَ السَّحَرَةُ لِمِيقَاتِ يَوْمٍ مَّعْلُومٍ(38)

Won si ko awon opidan jo ni asiko ti won fi adehun si ni ojo ti (gbogbo ilu) ti mo

وَقِيلَ لِلنَّاسِ هَلْ أَنتُم مُّجْتَمِعُونَ(39)

Won si wi fun awon eniyan pe: "Se eyin maa ko jo (sibe) bi

لَعَلَّنَا نَتَّبِعُ السَّحَرَةَ إِن كَانُوا هُمُ الْغَالِبِينَ(40)

Nitori ki a le tele awon opidan ti o ba je pe awon ni olubori

فَلَمَّا جَاءَ السَّحَرَةُ قَالُوا لِفِرْعَوْنَ أَئِنَّ لَنَا لَأَجْرًا إِن كُنَّا نَحْنُ الْغَالِبِينَ(41)

Nigba ti awon opidan de, won wi fun Fir‘aon pe: “Nje owo-oya kan wa fun wa, ti o ba je pe awa gan-an la je olubori?”

قَالَ نَعَمْ وَإِنَّكُمْ إِذًا لَّمِنَ الْمُقَرَّبِينَ(42)

(Fir‘aon) wi pe: “Bee ni, dajudaju nigba naa e maa wa ninu awon alasun-unmo (mi).”

قَالَ لَهُم مُّوسَىٰ أَلْقُوا مَا أَنتُم مُّلْقُونَ(43)

(Anabi) Musa so fun won pe: “E ju ohun ti e fe ju sile.”

فَأَلْقَوْا حِبَالَهُمْ وَعِصِيَّهُمْ وَقَالُوا بِعِزَّةِ فِرْعَوْنَ إِنَّا لَنَحْنُ الْغَالِبُونَ(44)

Won si ju awon okun won ati opa won sile. Won wi pe: “Pelu ogo Fir‘aon, dajudaju awa, awa ni olubori.”

فَأَلْقَىٰ مُوسَىٰ عَصَاهُ فَإِذَا هِيَ تَلْقَفُ مَا يَأْفِكُونَ(45)

Nigba naa, (Anabi) Musa ju opa re sile. O si n gbe ohun ti won pa niro kale mi kalokalo

فَأُلْقِيَ السَّحَرَةُ سَاجِدِينَ(46)

Nitori naa, ise iyanu (Anabi Musa) mu awon opidan wo lule, ti won fori kanle (fun Allahu)

قَالُوا آمَنَّا بِرَبِّ الْعَالَمِينَ(47)

Won so pe: "A gbagbo ninu Oluwa gbogbo eda

رَبِّ مُوسَىٰ وَهَارُونَ(48)

Oluwa (Anabi) Musa ati Harun

قَالَ آمَنتُمْ لَهُ قَبْلَ أَنْ آذَنَ لَكُمْ ۖ إِنَّهُ لَكَبِيرُكُمُ الَّذِي عَلَّمَكُمُ السِّحْرَ فَلَسَوْفَ تَعْلَمُونَ ۚ لَأُقَطِّعَنَّ أَيْدِيَكُمْ وَأَرْجُلَكُم مِّنْ خِلَافٍ وَلَأُصَلِّبَنَّكُمْ أَجْمَعِينَ(49)

Fir‘aon wi pe: “E gba A gbo siwaju ki ng to yonda fun yin! Dajudaju oun ni agba yin ti o ko yin ni idan pipa. Laipe e n bo wa mo. Dajudaju mo maa ge owo yin ati ese yin ni ipasipayo. Leyin naa, dajudaju mo maa kan gbogbo yin mogi.”

قَالُوا لَا ضَيْرَ ۖ إِنَّا إِلَىٰ رَبِّنَا مُنقَلِبُونَ(50)

(Awon opidan) so pe: “Ko si inira fun wa! Dajudaju awa yo si fabo si odo Oluwa wa

إِنَّا نَطْمَعُ أَن يَغْفِرَ لَنَا رَبُّنَا خَطَايَانَا أَن كُنَّا أَوَّلَ الْمُؤْمِنِينَ(51)

Dajudaju awa n reti pe Oluwa wa yoo se aforijin awon asise wa fun wa nitori pe awa je eni akoko (ti o je) onigbagbo ododo.”

۞ وَأَوْحَيْنَا إِلَىٰ مُوسَىٰ أَنْ أَسْرِ بِعِبَادِي إِنَّكُم مُّتَّبَعُونَ(52)

A fi imisi ranse si (Anabi) Musa pe: “Mu awon erusin Mi rin ni oru (nitori pe) dajudaju won yoo lepa yin.”

فَأَرْسَلَ فِرْعَوْنُ فِي الْمَدَائِنِ حَاشِرِينَ(53)

Fir‘aon si ran awon akonijo sinu awon ilu (lati so pe)

إِنَّ هَٰؤُلَاءِ لَشِرْذِمَةٌ قَلِيلُونَ(54)

Dajudaju awon (omo ’Isro’il) wonyi, ijo perete die ni won

وَإِنَّهُمْ لَنَا لَغَائِظُونَ(55)

Ati pe dajudaju won ti se ohun t’o n bi wa ninu

وَإِنَّا لَجَمِيعٌ حَاذِرُونَ(56)

Dajudaju gbogbo wa ni ki a si wa tifura-tifura

فَأَخْرَجْنَاهُم مِّن جَنَّاتٍ وَعُيُونٍ(57)

Nitori naa, A mu (ijo Fir‘aon) jade kuro ninu awon ogba oko ati iseleru omi

وَكُنُوزٍ وَمَقَامٍ كَرِيمٍ(58)

ati awon apoti-oro ati ibujokoo aponle

كَذَٰلِكَ وَأَوْرَثْنَاهَا بَنِي إِسْرَائِيلَ(59)

Bayen (loro ri). A si jogun re fun awon omo ’Isro’il

فَأَتْبَعُوهُم مُّشْرِقِينَ(60)

Won si lepa won ni asiko ti oorun yo

فَلَمَّا تَرَاءَى الْجَمْعَانِ قَالَ أَصْحَابُ مُوسَىٰ إِنَّا لَمُدْرَكُونَ(61)

Nigba ti ijo mejeeji rira won, awon ijo (Anabi) Musa so pe: “Dajudaju won yoo le wa ba.”

قَالَ كَلَّا ۖ إِنَّ مَعِيَ رَبِّي سَيَهْدِينِ(62)

(Anabi) Musa so pe: “Rara, dajudaju Oluwa mi n be pelu mi. O si maa fi ona mo mi.”

فَأَوْحَيْنَا إِلَىٰ مُوسَىٰ أَنِ اضْرِب بِّعَصَاكَ الْبَحْرَ ۖ فَانفَلَقَ فَكَانَ كُلُّ فِرْقٍ كَالطَّوْدِ الْعَظِيمِ(63)

A si fi imisi ranse si (Anabi) Musa pe: “Fi opa re na agbami okun.” (O fi na a). O si pin (si ona mejila). Ipin kookan si da bi apata nla

وَأَزْلَفْنَا ثَمَّ الْآخَرِينَ(64)

A si mu ijo keji (iyen, ijo Fir‘aon) sunmo ibe yen

وَأَنجَيْنَا مُوسَىٰ وَمَن مَّعَهُ أَجْمَعِينَ(65)

A gba (Anabi) Musa ati gbogbo awon t’o n be pelu re la patapata

ثُمَّ أَغْرَقْنَا الْآخَرِينَ(66)

Leyin naa, A te ijo keji ri (sinu agbami)

إِنَّ فِي ذَٰلِكَ لَآيَةً ۖ وَمَا كَانَ أَكْثَرُهُم مُّؤْمِنِينَ(67)

Dajudaju ami wa ninu iyen. Sibesibe opolopo won ko je onigbagbo ododo

وَإِنَّ رَبَّكَ لَهُوَ الْعَزِيزُ الرَّحِيمُ(68)

Dajudaju Oluwa re, Oun ma ni Alagbara, Asake-orun

وَاتْلُ عَلَيْهِمْ نَبَأَ إِبْرَاهِيمَ(69)

Ka iroyin (Anabi) ’Ibrohim fun won

إِذْ قَالَ لِأَبِيهِ وَقَوْمِهِ مَا تَعْبُدُونَ(70)

Nigba ti o so fun baba re ati awon eniyan re pe: “Ki ni nnkan ti e n josin fun na?”

قَالُوا نَعْبُدُ أَصْنَامًا فَنَظَلُّ لَهَا عَاكِفِينَ(71)

Won wi pe: “A n josin fun awon ere kan ni. A o si nii ye taku ti won lorun.”

قَالَ هَلْ يَسْمَعُونَكُمْ إِذْ تَدْعُونَ(72)

(Anabi ’Ibrohim) so pe: “Nje won n gbo oro yin nigba ti e ba n pe won

أَوْ يَنفَعُونَكُمْ أَوْ يَضُرُّونَ(73)

Tabi (se) won le se yin ni oore tabi won le fi inira kan yin?”

قَالُوا بَلْ وَجَدْنَا آبَاءَنَا كَذَٰلِكَ يَفْعَلُونَ(74)

Won wi pe: “Rara o! A ba awon baba wa, ti won n se bee ni”

قَالَ أَفَرَأَيْتُم مَّا كُنتُمْ تَعْبُدُونَ(75)

(Anabi ’Ibrohim) so pe: " E so fun mi, ki ni nnkan ti e n josin fun

أَنتُمْ وَآبَاؤُكُمُ الْأَقْدَمُونَ(76)

eyin ati awon baba yin isaaju

فَإِنَّهُمْ عَدُوٌّ لِّي إِلَّا رَبَّ الْعَالَمِينَ(77)

Dajudaju awon ni ota fun mi ayafi Oluwa gbogbo eda

الَّذِي خَلَقَنِي فَهُوَ يَهْدِينِ(78)

(Oun ni) Eni ti O seda mi. Nitori naa, O maa fi ona mo mi

وَالَّذِي هُوَ يُطْعِمُنِي وَيَسْقِينِ(79)

Eni t’O n fun mi ni jije, t’O n fun mi ni mimu

وَإِذَا مَرِضْتُ فَهُوَ يَشْفِينِ(80)

Ati pe nigba ti ara mi ko ba ya, Oun l’O n wo mi san

وَالَّذِي يُمِيتُنِي ثُمَّ يُحْيِينِ(81)

Eni ti O maa pa mi, leyin naa, O maa so mi di alaaye

وَالَّذِي أَطْمَعُ أَن يَغْفِرَ لِي خَطِيئَتِي يَوْمَ الدِّينِ(82)

Eni ti mo ni ireti si pe O maa fori awon asise mi jin mi ni Ojo Esan

رَبِّ هَبْ لِي حُكْمًا وَأَلْحِقْنِي بِالصَّالِحِينَ(83)

Oluwa mi, ta mi ni ore ipo Anabi. Da mi po mo awon eni rere

وَاجْعَل لِّي لِسَانَ صِدْقٍ فِي الْآخِرِينَ(84)

Je ki awon t’o n bo leyin (mi) maa soro mi pelu daadaa

وَاجْعَلْنِي مِن وَرَثَةِ جَنَّةِ النَّعِيمِ(85)

Se mi ni okan ninu awon olujogun Ogba Idera

وَاغْفِرْ لِأَبِي إِنَّهُ كَانَ مِنَ الضَّالِّينَ(86)

Ki O si forijin baba mi. Dajudaju o je okan ninu awon olusina

وَلَا تُخْزِنِي يَوْمَ يُبْعَثُونَ(87)

Ma se doju ti mi ni ojo ti won yoo gbe eda dide

يَوْمَ لَا يَنفَعُ مَالٌ وَلَا بَنُونَ(88)

Ojo ti dukia kan tabi awon omo ko nii sanfaani

إِلَّا مَنْ أَتَى اللَّهَ بِقَلْبٍ سَلِيمٍ(89)

Ayafi eni ti o ba de odo Allahu pelu okan mimo

وَأُزْلِفَتِ الْجَنَّةُ لِلْمُتَّقِينَ(90)

A maa mu Ogba Idera sunmo awon oluberu (Allahu)

وَبُرِّزَتِ الْجَحِيمُ لِلْغَاوِينَ(91)

Won si maa fi ina Jehim han awon olusina

وَقِيلَ لَهُمْ أَيْنَ مَا كُنتُمْ تَعْبُدُونَ(92)

won yo si so fun won pe: “Nibo ni nnkan ti e n josin fun wa?”

مِن دُونِ اللَّهِ هَلْ يَنصُرُونَكُمْ أَوْ يَنتَصِرُونَ(93)

(Nnkan ti e n josin fun) leyin Allahu, se won le ran yin lowo tabi se won le ran ara won lowo

فَكُبْكِبُوا فِيهَا هُمْ وَالْغَاوُونَ(94)

Won si maa taari gbogbo won sinu Ina; awon ati esu won

وَجُنُودُ إِبْلِيسَ أَجْمَعُونَ(95)

ati awon omo ogun ’Iblis patapata

قَالُوا وَهُمْ فِيهَا يَخْتَصِمُونَ(96)

(Awon alaigbagbo), nigba ti won ba n ba ara won jiyan ninu Ina, won a wi pe

تَاللَّهِ إِن كُنَّا لَفِي ضَلَالٍ مُّبِينٍ(97)

A fi Allahu bura, dajudaju awa kuku ti wa ninu isina ponnbele

إِذْ نُسَوِّيكُم بِرَبِّ الْعَالَمِينَ(98)

nigba ti a fi yin se akegbe fun Oluwa gbogbo eda

وَمَا أَضَلَّنَا إِلَّا الْمُجْرِمُونَ(99)

Ko si ohun ti o si wa lona bi ko se awon (esu) elese

فَمَا لَنَا مِن شَافِعِينَ(100)

Ko si si awon olusipe kan fun wa

وَلَا صَدِيقٍ حَمِيمٍ(101)

Ko tun si ore imule kan (fun wa)

فَلَوْ أَنَّ لَنَا كَرَّةً فَنَكُونَ مِنَ الْمُؤْمِنِينَ(102)

Ti o ba je pe ipada si ile aye wa fun wa ni, nigba naa awa iba wa ninu awon onigbagbo ododo

إِنَّ فِي ذَٰلِكَ لَآيَةً ۖ وَمَا كَانَ أَكْثَرُهُم مُّؤْمِنِينَ(103)

Dajudaju ami wa ninu iyen. Sibesibe opolopo won ni ko si je onigbagbo ododo

وَإِنَّ رَبَّكَ لَهُوَ الْعَزِيزُ الرَّحِيمُ(104)

Dajudaju Oluwa re, Oun ma ni Alagbara, Asake-orun

كَذَّبَتْ قَوْمُ نُوحٍ الْمُرْسَلِينَ(105)

Ijo (Anabi) Nuh pe awon Ojise ni opuro

إِذْ قَالَ لَهُمْ أَخُوهُمْ نُوحٌ أَلَا تَتَّقُونَ(106)

Nigba ti arakunrin won, (Anabi) Nuh, so pe: “Se e o nii beru (Allahu) ni

إِنِّي لَكُمْ رَسُولٌ أَمِينٌ(107)

Dajudaju emi ni Ojise olufokantan fun yin

فَاتَّقُوا اللَّهَ وَأَطِيعُونِ(108)

Nitori naa, e beru Allahu, ki e si tele mi

وَمَا أَسْأَلُكُمْ عَلَيْهِ مِنْ أَجْرٍ ۖ إِنْ أَجْرِيَ إِلَّا عَلَىٰ رَبِّ الْعَالَمِينَ(109)

Emi ko si beere owo-oya kan ni owo yin lori re. Ko si esan mi lodo eni kan afi lodo Oluwa gbogbo eda

فَاتَّقُوا اللَّهَ وَأَطِيعُونِ(110)

Nitori naa, e beru Allahu, ki e si tele mi.”

۞ قَالُوا أَنُؤْمِنُ لَكَ وَاتَّبَعَكَ الْأَرْذَلُونَ(111)

Won wi pe: “Se ki a gba o gbo nigba ti o je pe awon eniyan yepere l’o n tele o!?”

قَالَ وَمَا عِلْمِي بِمَا كَانُوا يَعْمَلُونَ(112)

O so pe: “Emi ko nimo si ohun ti won n se (leyin mi)

إِنْ حِسَابُهُمْ إِلَّا عَلَىٰ رَبِّي ۖ لَوْ تَشْعُرُونَ(113)

Ko si isiro-ise won lodo eni kan bi ko se lodo Oluwa mi, ti o ba je pe e ba fura

وَمَا أَنَا بِطَارِدِ الْمُؤْمِنِينَ(114)

Emi ko si nii le awon onigbagbo ododo danu

إِنْ أَنَا إِلَّا نَذِيرٌ مُّبِينٌ(115)

Emi ko si je kini kan bi ko se olukilo ponnbele.”

قَالُوا لَئِن لَّمْ تَنتَهِ يَا نُوحُ لَتَكُونَنَّ مِنَ الْمَرْجُومِينَ(116)

Won wi pe: “Dajudaju ti iwo Nuh ko ba jawo (nibi ipepe re) dajudaju o maa wa ninu awon ti a maa ju loko.”

قَالَ رَبِّ إِنَّ قَوْمِي كَذَّبُونِ(117)

O so pe: “Oluwa mi, dajudaju awon eniyan mi ti pe mi ni opuro

فَافْتَحْ بَيْنِي وَبَيْنَهُمْ فَتْحًا وَنَجِّنِي وَمَن مَّعِيَ مِنَ الْمُؤْمِنِينَ(118)

Nitori naa, sedajo taara laaarin emi ati awon. Ki o si la emi ati awon t’o wa pelu mi ninu awon onigbagbo ododo.”

فَأَنجَيْنَاهُ وَمَن مَّعَهُ فِي الْفُلْكِ الْمَشْحُونِ(119)

A la oun ati awon t’o wa pelu re ninu oko oju-omi t’o kun keke

ثُمَّ أَغْرَقْنَا بَعْدُ الْبَاقِينَ(120)

Leyin naa, A te awon t’o seku ri sinu omi

إِنَّ فِي ذَٰلِكَ لَآيَةً ۖ وَمَا كَانَ أَكْثَرُهُم مُّؤْمِنِينَ(121)

Dajudaju ami wa ninu iyen. Opolopo won ni ko si je onigbagbo ododo

وَإِنَّ رَبَّكَ لَهُوَ الْعَزِيزُ الرَّحِيمُ(122)

Dajudaju Oluwa re, Oun ma ni Alagbara, Asake-orun

كَذَّبَتْ عَادٌ الْمُرْسَلِينَ(123)

Awon iran ‘Ad pe awon Ojise ni opuro

إِذْ قَالَ لَهُمْ أَخُوهُمْ هُودٌ أَلَا تَتَّقُونَ(124)

Nigba ti arakunrin won, (Anabi) Hud, so pe: “Se e o nii beru (Allahu) ni

إِنِّي لَكُمْ رَسُولٌ أَمِينٌ(125)

Dajudaju emi ni Ojise olufokantan fun yin

فَاتَّقُوا اللَّهَ وَأَطِيعُونِ(126)

Nitori naa, e beru Allahu, ki e si tele mi

وَمَا أَسْأَلُكُمْ عَلَيْهِ مِنْ أَجْرٍ ۖ إِنْ أَجْرِيَ إِلَّا عَلَىٰ رَبِّ الْعَالَمِينَ(127)

Emi ko si beere owo-oya kan ni owo yin lori re. Ko si esan mi lodo eni kan afi lodo Oluwa gbogbo eda

أَتَبْنُونَ بِكُلِّ رِيعٍ آيَةً تَعْبَثُونَ(128)

Se e oo maa ko ile nla nla si awon aye giga (ki e le) maa fi awon olurekoja sefe

وَتَتَّخِذُونَ مَصَانِعَ لَعَلَّكُمْ تَخْلُدُونَ(129)

E si n ko awon ile nla nla bi eni pe e maa se gbere (nile aye yii)

وَإِذَا بَطَشْتُم بَطَشْتُمْ جَبَّارِينَ(130)

Nigba ti e ba si gba (eniyan mu lati fiya je won), e n gba won mu ni igbamu alailoju-aanu

فَاتَّقُوا اللَّهَ وَأَطِيعُونِ(131)

Nitori naa, e beru Allahu, ki e si tele mi

وَاتَّقُوا الَّذِي أَمَدَّكُم بِمَا تَعْلَمُونَ(132)

E beru Eni ti O ran yin lowo pelu ohun ti e mo

أَمَدَّكُم بِأَنْعَامٍ وَبَنِينَ(133)

O ran yin lowo pelu awon eran-osin ati awon omo

وَجَنَّاتٍ وَعُيُونٍ(134)

ati awon ogba oko pelu awon iseleru omi

إِنِّي أَخَافُ عَلَيْكُمْ عَذَابَ يَوْمٍ عَظِيمٍ(135)

Dajudaju emi n paya iya ojo nla fun yin.”

قَالُوا سَوَاءٌ عَلَيْنَا أَوَعَظْتَ أَمْ لَمْ تَكُن مِّنَ الْوَاعِظِينَ(136)

Won wi pe: “Bakan naa ni fun wa; yala o kilo fun wa tabi o o si ninu awon olukilo

إِنْ هَٰذَا إِلَّا خُلُقُ الْأَوَّلِينَ(137)

Eyi ko je kini kan bi ko se iwa awon eni akoko

وَمَا نَحْنُ بِمُعَذَّبِينَ(138)

Won ko si nii je wa niya.”

فَكَذَّبُوهُ فَأَهْلَكْنَاهُمْ ۗ إِنَّ فِي ذَٰلِكَ لَآيَةً ۖ وَمَا كَانَ أَكْثَرُهُم مُّؤْمِنِينَ(139)

Nitori naa, won pe e ni opuro. A si pa won run. Dajudaju ami wa ninu iyen. Opolopo won ni ko si je onigbagbo ododo

وَإِنَّ رَبَّكَ لَهُوَ الْعَزِيزُ الرَّحِيمُ(140)

Dajudaju Oluwa re, Oun ma ni Alagbara, Asake-orun

كَذَّبَتْ ثَمُودُ الْمُرْسَلِينَ(141)

Awon iran Thamud pe awon Ojise ni opuro

إِذْ قَالَ لَهُمْ أَخُوهُمْ صَالِحٌ أَلَا تَتَّقُونَ(142)

Nigba ti arakunrin won, (Anabi) Solih, so pe: “Se e o nii beru (Allahu) ni

إِنِّي لَكُمْ رَسُولٌ أَمِينٌ(143)

Dajudaju emi ni Ojise olufokantan fun yin

فَاتَّقُوا اللَّهَ وَأَطِيعُونِ(144)

Nitori naa, e beru Allahu, ki e si tele mi

وَمَا أَسْأَلُكُمْ عَلَيْهِ مِنْ أَجْرٍ ۖ إِنْ أَجْرِيَ إِلَّا عَلَىٰ رَبِّ الْعَالَمِينَ(145)

Emi ko si beere owo-oya kan ni owo yin lori re. Ko si esan mi lodo eni kan afi lodo Oluwa gbogbo eda

أَتُتْرَكُونَ فِي مَا هَاهُنَا آمِنِينَ(146)

Se ki won fi yin sile sibi nnkan ti o wa (nile aye) nibi yii (ninu igbadun aye, ki e je) olufokanbale

فِي جَنَّاتٍ وَعُيُونٍ(147)

ninu awon ogba oko ati iseleru omi

وَزُرُوعٍ وَنَخْلٍ طَلْعُهَا هَضِيمٌ(148)

ati oko irugbin pelu igi dabinu ti ogomo re tutu

وَتَنْحِتُونَ مِنَ الْجِبَالِ بُيُوتًا فَارِهِينَ(149)

E si n gbe awon ile sinu awon apata (gege bi) akose-mose

فَاتَّقُوا اللَّهَ وَأَطِيعُونِ(150)

Nitori naa, e beru Allahu, ki e si tele mi

وَلَا تُطِيعُوا أَمْرَ الْمُسْرِفِينَ(151)

Ki e si ma se tele ase awon alaseju

الَّذِينَ يُفْسِدُونَ فِي الْأَرْضِ وَلَا يُصْلِحُونَ(152)

awon t’o n sebaje lori ile, ti won ko si se rere.”

قَالُوا إِنَّمَا أَنتَ مِنَ الْمُسَحَّرِينَ(153)

Won wi pe: “Iwo kuku wa ninu awon eleedi

مَا أَنتَ إِلَّا بَشَرٌ مِّثْلُنَا فَأْتِ بِآيَةٍ إِن كُنتَ مِنَ الصَّادِقِينَ(154)

Iwo ko si je kini kan bi ko se abara bi iru wa. Nitori naa, mu ami kan wa ti o ba wa ninu awon olododo.”

قَالَ هَٰذِهِ نَاقَةٌ لَّهَا شِرْبٌ وَلَكُمْ شِرْبُ يَوْمٍ مَّعْلُومٍ(155)

O so pe: “Eyi ni abo rakunmi kan. Omi wa fun ohun, omi si wa fun eyin naa ni ojo ti a ti mo

وَلَا تَمَسُّوهَا بِسُوءٍ فَيَأْخُذَكُمْ عَذَابُ يَوْمٍ عَظِيمٍ(156)

E ma se fi aburu kan kan an nitori ki iya ojo nla ma baa je yin.”

فَعَقَرُوهَا فَأَصْبَحُوا نَادِمِينَ(157)

Won si gun un pa. Nitori naa, won si di alabaamo

فَأَخَذَهُمُ الْعَذَابُ ۗ إِنَّ فِي ذَٰلِكَ لَآيَةً ۖ وَمَا كَانَ أَكْثَرُهُم مُّؤْمِنِينَ(158)

Iya naa je won. Dajudaju ami wa ninu iyen. Opolopo won ni ko si je onigbagbo ododo

وَإِنَّ رَبَّكَ لَهُوَ الْعَزِيزُ الرَّحِيمُ(159)

Dajudaju Oluwa re, Oun ma ni Alagbara, Asake-orun

كَذَّبَتْ قَوْمُ لُوطٍ الْمُرْسَلِينَ(160)

Ijo Lut pe awon Ojise ni opuro

إِذْ قَالَ لَهُمْ أَخُوهُمْ لُوطٌ أَلَا تَتَّقُونَ(161)

Nigba ti arakunrin won, (Anabi) Lut, so pe: “Se e o nii beru (Allahu) ni

إِنِّي لَكُمْ رَسُولٌ أَمِينٌ(162)

Dajudaju emi ni Ojise olufokantan fun yin

فَاتَّقُوا اللَّهَ وَأَطِيعُونِ(163)

Nitori naa, e beru Allahu, ki e si tele mi

وَمَا أَسْأَلُكُمْ عَلَيْهِ مِنْ أَجْرٍ ۖ إِنْ أَجْرِيَ إِلَّا عَلَىٰ رَبِّ الْعَالَمِينَ(164)

Emi ko si beere owo-oya kan ni owo yin lori re. Ko si esan mi lodo eni kan afi lodo Oluwa gbogbo eda

أَتَأْتُونَ الذُّكْرَانَ مِنَ الْعَالَمِينَ(165)

Se awon okunrin ninu eda ni eyin okunrin yoo lo maa ba (fun adun ibalopo)

وَتَذَرُونَ مَا خَلَقَ لَكُمْ رَبُّكُم مِّنْ أَزْوَاجِكُم ۚ بَلْ أَنتُمْ قَوْمٌ عَادُونَ(166)

E si n pa ohun ti Oluwa yin da fun yin ti ninu awon iyawo yin! Ani se, ijo alakoyo ni eyin.”

قَالُوا لَئِن لَّمْ تَنتَهِ يَا لُوطُ لَتَكُونَنَّ مِنَ الْمُخْرَجِينَ(167)

Won wi pe: “Ti iwo Lut ko ba jawo (nibi ipepe re) dajudaju o maa wa ninu awon ti a maa le jade kuro ninu ilu.”

قَالَ إِنِّي لِعَمَلِكُم مِّنَ الْقَالِينَ(168)

O so pe: "Dajudaju emi wa ninu awon olubinu si ise (aburu) owo yin

رَبِّ نَجِّنِي وَأَهْلِي مِمَّا يَعْمَلُونَ(169)

Oluwa mi, la emi ati awon eniyan mi nibi ohun ti won n se nise (aburu)

فَنَجَّيْنَاهُ وَأَهْلَهُ أَجْمَعِينَ(170)

Nitori naa, A la oun ati awon eniyan re patapata

إِلَّا عَجُوزًا فِي الْغَابِرِينَ(171)

Afi arugbobinrin kan ti o wa ninu awon t’o se ku leyin (laaarin awon ti A pare)

ثُمَّ دَمَّرْنَا الْآخَرِينَ(172)

Leyin naa, A pa awon yooku run

وَأَمْطَرْنَا عَلَيْهِم مَّطَرًا ۖ فَسَاءَ مَطَرُ الْمُنذَرِينَ(173)

A ro ojo le won lori taara. Ojo awon ti A kilo fun si buru

إِنَّ فِي ذَٰلِكَ لَآيَةً ۖ وَمَا كَانَ أَكْثَرُهُم مُّؤْمِنِينَ(174)

Dajudaju ami wa ninu iyen. Opolopo won ni ko si je onigbagbo ododo

وَإِنَّ رَبَّكَ لَهُوَ الْعَزِيزُ الرَّحِيمُ(175)

Dajudaju Oluwa re, Oun ma ni Alagbara, Asake-orun

كَذَّبَ أَصْحَابُ الْأَيْكَةِ الْمُرْسَلِينَ(176)

Awon ara ’Aekah pe awon Ojise ni opuro

إِذْ قَالَ لَهُمْ شُعَيْبٌ أَلَا تَتَّقُونَ(177)

Nigba ti arakunrin won, (Anabi) Su‘aeb, so pe: “Se eyin ko nii beru (Allahu) ni

إِنِّي لَكُمْ رَسُولٌ أَمِينٌ(178)

Dajudaju emi ni Ojise olufokantan fun yin

فَاتَّقُوا اللَّهَ وَأَطِيعُونِ(179)

Nitori naa, e beru Allahu, ki e si tele mi

وَمَا أَسْأَلُكُمْ عَلَيْهِ مِنْ أَجْرٍ ۖ إِنْ أَجْرِيَ إِلَّا عَلَىٰ رَبِّ الْعَالَمِينَ(180)

Emi ko si beere owo-oya kan ni owo yin lori re. Ko si esan mi lodo eni kan afi lodo Oluwa gbogbo eda

۞ أَوْفُوا الْكَيْلَ وَلَا تَكُونُوا مِنَ الْمُخْسِرِينَ(181)

E won osuwon kun. Ki e si ma se wa ninu awon oludosuwonku

وَزِنُوا بِالْقِسْطَاسِ الْمُسْتَقِيمِ(182)

E fi iwon t’o to won nnkan

وَلَا تَبْخَسُوا النَّاسَ أَشْيَاءَهُمْ وَلَا تَعْثَوْا فِي الْأَرْضِ مُفْسِدِينَ(183)

E ma se din nnkan awon eniyan ku. Ki e si ma se huwa aburu lori ile ni ti obileje

وَاتَّقُوا الَّذِي خَلَقَكُمْ وَالْجِبِلَّةَ الْأَوَّلِينَ(184)

Ki e si beru Eni ti O da yin ati awon iran akoko.”

قَالُوا إِنَّمَا أَنتَ مِنَ الْمُسَحَّرِينَ(185)

Won wi pe: “Iwo kuku wa ninu awon eleedi

وَمَا أَنتَ إِلَّا بَشَرٌ مِّثْلُنَا وَإِن نَّظُنُّكَ لَمِنَ الْكَاذِبِينَ(186)

Iwo ko si je kini kan bi ko se abara bi iru wa. Ati pe a o ro o si kini kan bi ko se pe o wa ninu awon opuro

فَأَسْقِطْ عَلَيْنَا كِسَفًا مِّنَ السَّمَاءِ إِن كُنتَ مِنَ الصَّادِقِينَ(187)

Nitori naa, je ki apa kan ninu sanmo ya lu wa mole, ti o ba wa ninu awon olododo.”

قَالَ رَبِّي أَعْلَمُ بِمَا تَعْمَلُونَ(188)

O so pe: “Oluwa mi nimo julo nipa ohun ti e n se nise

فَكَذَّبُوهُ فَأَخَذَهُمْ عَذَابُ يَوْمِ الظُّلَّةِ ۚ إِنَّهُ كَانَ عَذَابَ يَوْمٍ عَظِيمٍ(189)

Won si pe e ni opuro. Nitori naa, iya ojo esujo si je won. Dajudaju o je iya ojo nla

إِنَّ فِي ذَٰلِكَ لَآيَةً ۖ وَمَا كَانَ أَكْثَرُهُم مُّؤْمِنِينَ(190)

Dajudaju ami wa ninu iyen. Opolopo won ni ko si je onigbagbo ododo

وَإِنَّ رَبَّكَ لَهُوَ الْعَزِيزُ الرَّحِيمُ(191)

Dajudaju Oluwa re, Oun ma ni Alagbara, Asake-orun

وَإِنَّهُ لَتَنزِيلُ رَبِّ الْعَالَمِينَ(192)

Dajudaju al-Ƙur’an, won so o kale ni lati odo Oluwa gbogbo eda

نَزَلَ بِهِ الرُّوحُ الْأَمِينُ(193)

Molaika Jibril, olufokantan l’o so o kale

عَلَىٰ قَلْبِكَ لِتَكُونَ مِنَ الْمُنذِرِينَ(194)

sinu okan re nitori ki o le wa ninu awon olukilo

بِلِسَانٍ عَرَبِيٍّ مُّبِينٍ(195)

pelu ede Larubawa ponnbele

وَإِنَّهُ لَفِي زُبُرِ الْأَوَّلِينَ(196)

Dajudaju (oro nipa re) ti wa ninu ipin-ipin Tira awon eni akoko

أَوَلَمْ يَكُن لَّهُمْ آيَةً أَن يَعْلَمَهُ عُلَمَاءُ بَنِي إِسْرَائِيلَ(197)

Se ko je ami kan fun won pe awon onimo (ninu) awon omo ’Isro’il nimo (si asoole nipa) re (ninu tira owo won)

وَلَوْ نَزَّلْنَاهُ عَلَىٰ بَعْضِ الْأَعْجَمِينَ(198)

Ti o ba je pe A so o kale fun apa kan awon elede miiran ni

فَقَرَأَهُ عَلَيْهِم مَّا كَانُوا بِهِ مُؤْمِنِينَ(199)

ti o si ke e fun won, won ko nii gba a gbo ni ododo

كَذَٰلِكَ سَلَكْنَاهُ فِي قُلُوبِ الْمُجْرِمِينَ(200)

Bayen ni A se mu (atako) wo inu okan awon elese

لَا يُؤْمِنُونَ بِهِ حَتَّىٰ يَرَوُا الْعَذَابَ الْأَلِيمَ(201)

Won ko nii gba a gbo ni ododo titi won yoo fi ri iya eleta-elero

فَيَأْتِيَهُم بَغْتَةً وَهُمْ لَا يَشْعُرُونَ(202)

(Iya naa) yoo de ba won ni ojiji; won ko si nii fura

فَيَقُولُوا هَلْ نَحْنُ مُنظَرُونَ(203)

Nigba naa ni won yoo wi pe: "Nje won le lo wa lara bi

أَفَبِعَذَابِنَا يَسْتَعْجِلُونَ(204)

Se iya Wa ni won n wa pelu ikanju

أَفَرَأَيْتَ إِن مَّتَّعْنَاهُمْ سِنِينَ(205)

So fun Mi ti A ba fun won ni igbadun aye fun odun gbooro

ثُمَّ جَاءَهُم مَّا كَانُوا يُوعَدُونَ(206)

Leyin naa, ki ohun ti A n se ni adehun fun won de ba won

مَا أَغْنَىٰ عَنْهُم مَّا كَانُوا يُمَتَّعُونَ(207)

Ohun ti A se ni igbadun fun won ko si nii ro won loro

وَمَا أَهْلَكْنَا مِن قَرْيَةٍ إِلَّا لَهَا مُنذِرُونَ(208)

A o si pa ilu kan run afi ki won ti ni awon olukilo

ذِكْرَىٰ وَمَا كُنَّا ظَالِمِينَ(209)

Iranti (de fun won se). Ati pe Awa ki i se alabosi

وَمَا تَنَزَّلَتْ بِهِ الشَّيَاطِينُ(210)

Ki i se awon esu ni won so (al-Ƙur’an) kale

وَمَا يَنبَغِي لَهُمْ وَمَا يَسْتَطِيعُونَ(211)

Ko ye fun won. Won ko si lagbara re

إِنَّهُمْ عَنِ السَّمْعِ لَمَعْزُولُونَ(212)

Dajudaju A ti mu won takete si gbigbo re (lati oju sanmo)

فَلَا تَدْعُ مَعَ اللَّهِ إِلَٰهًا آخَرَ فَتَكُونَ مِنَ الْمُعَذَّبِينَ(213)

Nitori naa, ma se pe olohun miiran mo Allahu, nitori ki iwo ma baa wa ninu awon ti A maa je niya

وَأَنذِرْ عَشِيرَتَكَ الْأَقْرَبِينَ(214)

Ki o si kilo fun awon ebi re, t’o sunmo julo

وَاخْفِضْ جَنَاحَكَ لِمَنِ اتَّبَعَكَ مِنَ الْمُؤْمِنِينَ(215)

Ki o si re apa re nile fun awon t’o tele o ninu awon onigbagbo ododo

فَإِنْ عَصَوْكَ فَقُلْ إِنِّي بَرِيءٌ مِّمَّا تَعْمَلُونَ(216)

Ti won ba si yapa (ase) re, so pe: “Dajudaju emi yowo yose ninu ohun ti e n se (nise aburu).”

وَتَوَكَّلْ عَلَى الْعَزِيزِ الرَّحِيمِ(217)

Ki o si gbarale Alagbara, Asake-orun

الَّذِي يَرَاكَ حِينَ تَقُومُ(218)

Eni t’O n ri o nigba ti o n dide naro (fun irun kiki)

وَتَقَلُّبَكَ فِي السَّاجِدِينَ(219)

ati iyirapada re (fun rukuu ati iforikanle) laaarin awon oluforikanle

إِنَّهُ هُوَ السَّمِيعُ الْعَلِيمُ(220)

Dajudaju Oun ma ni Olugbo, Onimo

هَلْ أُنَبِّئُكُمْ عَلَىٰ مَن تَنَزَّلُ الشَّيَاطِينُ(221)

Se ki ng so eni ti awon esu n sokale wa ba

تَنَزَّلُ عَلَىٰ كُلِّ أَفَّاكٍ أَثِيمٍ(222)

Won n sokale wa ba gbogbo awon opuro, elese

يُلْقُونَ السَّمْعَ وَأَكْثَرُهُمْ كَاذِبُونَ(223)

(Awon esu) n deti (si iro sanmo). Opolopo won si ni opuro

وَالشُّعَرَاءُ يَتَّبِعُهُمُ الْغَاوُونَ(224)

Awon elewi, awon olusina l’o n tele won

أَلَمْ تَرَ أَنَّهُمْ فِي كُلِّ وَادٍ يَهِيمُونَ(225)

Se o o ri i pe gbogbo ogbun oro ni won n tenu bo ni

وَأَنَّهُمْ يَقُولُونَ مَا لَا يَفْعَلُونَ(226)

Ati pe dajudaju won n so ohun ti won ko nii se

إِلَّا الَّذِينَ آمَنُوا وَعَمِلُوا الصَّالِحَاتِ وَذَكَرُوا اللَّهَ كَثِيرًا وَانتَصَرُوا مِن بَعْدِ مَا ظُلِمُوا ۗ وَسَيَعْلَمُ الَّذِينَ ظَلَمُوا أَيَّ مُنقَلَبٍ يَنقَلِبُونَ(227)

Afi awon t’o gbagbo ni ododo, ti won se ise rere, ti won ranti Allahu ni opolopo, ti won si jaja gbara leyin ti won ti sabosi si won. Awon t’o sabosi si maa mo iru ikangun ti won maa gunle si


المزيد من السور باللغة اليوربا:

سورة البقرة آل عمران سورة النساء
سورة المائدة سورة يوسف سورة ابراهيم
سورة الحجر سورة الكهف سورة مريم
سورة السجدة سورة يس سورة الدخان
سورة النجم سورة الرحمن سورة الواقعة
سورة الحشر سورة الملك سورة الحاقة

تحميل سورة الشعراء بصوت أشهر القراء :

قم باختيار القارئ للاستماع و تحميل سورة الشعراء كاملة بجودة عالية
سورة الشعراء أحمد العجمي
أحمد العجمي
سورة الشعراء خالد الجليل
خالد الجليل
سورة الشعراء سعد الغامدي
سعد الغامدي
سورة الشعراء سعود الشريم
سعود الشريم
سورة الشعراء عبد الباسط عبد الصمد
عبد الباسط
سورة الشعراء عبد الله عواد الجهني
عبد الله الجهني
سورة الشعراء علي الحذيفي
علي الحذيفي
سورة الشعراء فارس عباد
فارس عباد
سورة الشعراء ماهر المعيقلي
ماهر المعيقلي
سورة الشعراء محمد جبريل
محمد جبريل
سورة الشعراء محمد صديق المنشاوي
المنشاوي
سورة الشعراء الحصري
الحصري
سورة الشعراء العفاسي
مشاري العفاسي
سورة الشعراء ناصر القطامي
ناصر القطامي
سورة الشعراء ياسر الدوسري
ياسر الدوسري



Saturday, May 4, 2024

لا تنسنا من دعوة صالحة بظهر الغيب