Surah Yusuf with Yoruba

  1. Surah mp3
  2. More
  3. Yoruba
The Holy Quran | Quran translation | Language Yoruba | Surah Yusuf | يوسف - Ayat Count 111 - The number of the surah in moshaf: 12 - The meaning of the surah in English: Joseph.

الر ۚ تِلْكَ آيَاتُ الْكِتَابِ الْمُبِينِ(1)

 ’Alif lam ro. Iwonyi ni awon ayah Tira t’o yanju oro eda

إِنَّا أَنزَلْنَاهُ قُرْآنًا عَرَبِيًّا لَّعَلَّكُمْ تَعْقِلُونَ(2)

 Dajudaju Awa so o kale ni nnkan kike ni ede Larubawa nitori ki e le se laakaye

نَحْنُ نَقُصُّ عَلَيْكَ أَحْسَنَ الْقَصَصِ بِمَا أَوْحَيْنَا إِلَيْكَ هَٰذَا الْقُرْآنَ وَإِن كُنتَ مِن قَبْلِهِ لَمِنَ الْغَافِلِينَ(3)

 Awa n so itan t’o dara julo fun o pelu ohun ti A fi ranse si o (ninu imisi) al-Ƙur’an yii, bi o tile je pe siwaju imisi naa iwo wa lara awon ti ko nimo (nipa re)

إِذْ قَالَ يُوسُفُ لِأَبِيهِ يَا أَبَتِ إِنِّي رَأَيْتُ أَحَدَ عَشَرَ كَوْكَبًا وَالشَّمْسَ وَالْقَمَرَ رَأَيْتُهُمْ لِي سَاجِدِينَ(4)

 (Ranti) nigba ti (Anabi) Yusuf so fun baba re pe: “Baba mi, dajudaju emi (lalaa) ri awon irawo mokanla, oorun ati osupa. Mo ri won ti won fori kanle fun mi.”

قَالَ يَا بُنَيَّ لَا تَقْصُصْ رُؤْيَاكَ عَلَىٰ إِخْوَتِكَ فَيَكِيدُوا لَكَ كَيْدًا ۖ إِنَّ الشَّيْطَانَ لِلْإِنسَانِ عَدُوٌّ مُّبِينٌ(5)

 O so pe: "Omo mi, ma se ro ala re fun awon obakan re nitori ki won ma baa dete si o. Dajudaju Esu ni ota ponnbele fun eniyan

وَكَذَٰلِكَ يَجْتَبِيكَ رَبُّكَ وَيُعَلِّمُكَ مِن تَأْوِيلِ الْأَحَادِيثِ وَيُتِمُّ نِعْمَتَهُ عَلَيْكَ وَعَلَىٰ آلِ يَعْقُوبَ كَمَا أَتَمَّهَا عَلَىٰ أَبَوَيْكَ مِن قَبْلُ إِبْرَاهِيمَ وَإِسْحَاقَ ۚ إِنَّ رَبَّكَ عَلِيمٌ حَكِيمٌ(6)

 Bayen ni Oluwa re yoo se sa o lesa. O maa fi itumo ala mo o. O si maa pe idera Re fun iwo ati awon ebi Ya‘ƙub, gege bi O se pe e siwaju fun awon baba re mejeeji, (Anabi) ’Ibrohim ati ’Ishaƙ. Dajudaju Oluwa re ni Onimo, Ologbon

۞ لَّقَدْ كَانَ فِي يُوسُفَ وَإِخْوَتِهِ آيَاتٌ لِّلسَّائِلِينَ(7)

 Dajudaju awon ami (ariwoye) n be fun awon onibeeere nipa (itan Anabi) Yusuf ati awon obakan re

إِذْ قَالُوا لَيُوسُفُ وَأَخُوهُ أَحَبُّ إِلَىٰ أَبِينَا مِنَّا وَنَحْنُ عُصْبَةٌ إِنَّ أَبَانَا لَفِي ضَلَالٍ مُّبِينٍ(8)

 (Ranti) nigba ti won so pe: "Dajudaju Yusuf ati omo-iya re ni baba wa nifee si ju awa. Opo eniyan si ni awa. Dajudaju baba wa ma ti wa ninu asise ponnbele

اقْتُلُوا يُوسُفَ أَوِ اطْرَحُوهُ أَرْضًا يَخْلُ لَكُمْ وَجْهُ أَبِيكُمْ وَتَكُونُوا مِن بَعْدِهِ قَوْمًا صَالِحِينَ(9)

 E pa Yusuf tabi ki e lo gbe e junu si ile (miiran) nitori ki baba yin le roju gbo tiyin. E si maa di eniyan rere leyin re

قَالَ قَائِلٌ مِّنْهُمْ لَا تَقْتُلُوا يُوسُفَ وَأَلْقُوهُ فِي غَيَابَتِ الْجُبِّ يَلْتَقِطْهُ بَعْضُ السَّيَّارَةِ إِن كُنتُمْ فَاعِلِينَ(10)

 Onsoro kan ninu won so pe: "E ma se pa Yusuf. Ti o ba je pe e sa fe wa nnkan se (si oro re), e gbe e ju sinu isaleesale kannga nitori ki apa kan ninu awon onirin-ajo le baa he e lo

قَالُوا يَا أَبَانَا مَا لَكَ لَا تَأْمَنَّا عَلَىٰ يُوسُفَ وَإِنَّا لَهُ لَنَاصِحُونَ(11)

 Won so pe: “Baba wa, ki ni ko mu o fi okan tan wa lori Yusuf. Dajudaju awa si maa je olutoju re

أَرْسِلْهُ مَعَنَا غَدًا يَرْتَعْ وَيَلْعَبْ وَإِنَّا لَهُ لَحَافِظُونَ(12)

 Je ki o ba wa lo ni ola nitori ki o le dara ya, ki o si le sere. Ati pe dajudaju awa ni oluso fun un.”

قَالَ إِنِّي لَيَحْزُنُنِي أَن تَذْهَبُوا بِهِ وَأَخَافُ أَن يَأْكُلَهُ الذِّئْبُ وَأَنتُمْ عَنْهُ غَافِلُونَ(13)

 O so pe: “Dajudaju o maa ba mi ninu je pe ki e mu u lo. Mo si n paya ki ikoko ma lo pa a je nigba ti eyin ba gbagbe re (sibi kan).”

قَالُوا لَئِنْ أَكَلَهُ الذِّئْبُ وَنَحْنُ عُصْبَةٌ إِنَّا إِذًا لَّخَاسِرُونَ(14)

 Won so pe: “Ti ikoko ba fi pa a je, opo eniyan si ni wa, dajudaju awa nigba naa ni eni ofo.”

فَلَمَّا ذَهَبُوا بِهِ وَأَجْمَعُوا أَن يَجْعَلُوهُ فِي غَيَابَتِ الْجُبِّ ۚ وَأَوْحَيْنَا إِلَيْهِ لَتُنَبِّئَنَّهُم بِأَمْرِهِمْ هَٰذَا وَهُمْ لَا يَشْعُرُونَ(15)

 Nigba ti won mu un lo tan, won panupo pe ki awon ju u si isaleesale kannga. A si fi imisi ranse si Yusuf pe: “Dajudaju iwo yoo fun won ni iro nipa oro won yii nigba ti won ko nii fura.”

وَجَاءُوا أَبَاهُمْ عِشَاءً يَبْكُونَ(16)

 Won de ba baba won ni asale, ti won n sunkun

قَالُوا يَا أَبَانَا إِنَّا ذَهَبْنَا نَسْتَبِقُ وَتَرَكْنَا يُوسُفَ عِندَ مَتَاعِنَا فَأَكَلَهُ الذِّئْبُ ۖ وَمَا أَنتَ بِمُؤْمِنٍ لَّنَا وَلَوْ كُنَّا صَادِقِينَ(17)

 Won so pe: “Baba wa, awa lo dije ere sisa. A si fi Yusuf sile sibi awon eru wa. Nigba naa ni ikoko pa a je. Iwo ko si nii gba wa gbo, awa ibaa je olododo.”

وَجَاءُوا عَلَىٰ قَمِيصِهِ بِدَمٍ كَذِبٍ ۚ قَالَ بَلْ سَوَّلَتْ لَكُمْ أَنفُسُكُمْ أَمْرًا ۖ فَصَبْرٌ جَمِيلٌ ۖ وَاللَّهُ الْمُسْتَعَانُ عَلَىٰ مَا تَصِفُونَ(18)

 Won de pelu eje iro lara ewu re. (Anabi Ya‘ƙub) so pe: "Rara o, emi yin l’o se oran kan losoo fun yin. Nitori naa, suuru abiyi (loro mi kan). Allahu ni Oluranlowo lori ohun ti e n royin

وَجَاءَتْ سَيَّارَةٌ فَأَرْسَلُوا وَارِدَهُمْ فَأَدْلَىٰ دَلْوَهُ ۖ قَالَ يَا بُشْرَىٰ هَٰذَا غُلَامٌ ۚ وَأَسَرُّوهُ بِضَاعَةً ۚ وَاللَّهُ عَلِيمٌ بِمَا يَعْمَلُونَ(19)

 Awon onirin-ajo kan si de. Won ran aponmi won (ni omi). O si ju doro re sinu kannga. (Yusuf si diro mo okun doro bo sita. Aponmi si) so pe: "Ire idunnu re e! Eyi ni omodekunrin." Won si fi pamo fun tita (bi oja). Allahu si ni Onimo nipa ohun ti won n se nise

وَشَرَوْهُ بِثَمَنٍ بَخْسٍ دَرَاهِمَ مَعْدُودَةٍ وَكَانُوا فِيهِ مِنَ الزَّاهِدِينَ(20)

 Won ta a ni edinwo pelu owo diriham t’o niye. Won si je eni t’o mu un bin-intin

وَقَالَ الَّذِي اشْتَرَاهُ مِن مِّصْرَ لِامْرَأَتِهِ أَكْرِمِي مَثْوَاهُ عَسَىٰ أَن يَنفَعَنَا أَوْ نَتَّخِذَهُ وَلَدًا ۚ وَكَذَٰلِكَ مَكَّنَّا لِيُوسُفَ فِي الْأَرْضِ وَلِنُعَلِّمَهُ مِن تَأْوِيلِ الْأَحَادِيثِ ۚ وَاللَّهُ غَالِبٌ عَلَىٰ أَمْرِهِ وَلَٰكِنَّ أَكْثَرَ النَّاسِ لَا يَعْلَمُونَ(21)

 Eni ti o ra a ni (ilu) Misro so fun aya re pe: “Se ibugbe re daadaa. O sunmo ki o wulo fun wa tabi ki a fi somo.” Bayen ni A se fi aye gba Yusuf lori ile. Ati pe ki A tun le fi itumo ala mo on. Allahu ni Olubori lori ase Re, sugbon opolopo eniyan ni ko mo

وَلَمَّا بَلَغَ أَشُدَّهُ آتَيْنَاهُ حُكْمًا وَعِلْمًا ۚ وَكَذَٰلِكَ نَجْزِي الْمُحْسِنِينَ(22)

 Nigba ti o di gende tan, A fun un ni ogbon ijinle ati imo. Bayen ni A se n san awon oluse-rere ni esan rere

وَرَاوَدَتْهُ الَّتِي هُوَ فِي بَيْتِهَا عَن نَّفْسِهِ وَغَلَّقَتِ الْأَبْوَابَ وَقَالَتْ هَيْتَ لَكَ ۚ قَالَ مَعَاذَ اللَّهِ ۖ إِنَّهُ رَبِّي أَحْسَنَ مَثْوَايَ ۖ إِنَّهُ لَا يُفْلِحُ الظَّالِمُونَ(23)

 Obinrin ti Yusuf wa ninu ile re si jireebe fun ere ife lodo re. O si ti gbogbo ilekun pa. O so pe: “Sunmo mi.” (Yusuf) so pe: “Mo sadi Allahu. Dajudaju oko re ni oga mi. O si se ibugbe mi daadaa. Dajudaju awon alabosi ko nii jere.”

وَلَقَدْ هَمَّتْ بِهِ ۖ وَهَمَّ بِهَا لَوْلَا أَن رَّأَىٰ بُرْهَانَ رَبِّهِ ۚ كَذَٰلِكَ لِنَصْرِفَ عَنْهُ السُّوءَ وَالْفَحْشَاءَ ۚ إِنَّهُ مِنْ عِبَادِنَا الْمُخْلَصِينَ(24)

 (Obinrin naa) kuku gbero ere ife si i. Oun naa gbero re, Ti ki i ba se pe o ri eri Oluwa re (pe haramu ni sina, iba sunmo on). Bayen ni (oro naa ri) nitori ki A le seri aburu ati sina sise kuro lodo re. Dajudaju o wa ninu awon erusin Wa, awon eni esa

وَاسْتَبَقَا الْبَابَ وَقَدَّتْ قَمِيصَهُ مِن دُبُرٍ وَأَلْفَيَا سَيِّدَهَا لَدَى الْبَابِ ۚ قَالَتْ مَا جَزَاءُ مَنْ أَرَادَ بِأَهْلِكَ سُوءًا إِلَّا أَن يُسْجَنَ أَوْ عَذَابٌ أَلِيمٌ(25)

 Awon mejeeji sare lo sibi ilekun. (Obinrin yii) si fa ewu (Yusuf) ya leyin. Awon mejeeji si ba oga re lenu ona. (Obinrin yii) si so pe: “Ki ni esan fun eni ti o gbero aburu si ara ile re bi ko se pe ki a so o sinu ogba ewon tabi iya eleta-elero.”

قَالَ هِيَ رَاوَدَتْنِي عَن نَّفْسِي ۚ وَشَهِدَ شَاهِدٌ مِّنْ أَهْلِهَا إِن كَانَ قَمِيصُهُ قُدَّ مِن قُبُلٍ فَصَدَقَتْ وَهُوَ مِنَ الْكَاذِبِينَ(26)

 (Yusuf) so pe: “Oun l’o jireebe fun ere ife lodo mi.” Elerii kan ninu ara ile (obinrin naa) si jerii pe: "Ti o ba je pe won fa ewu re ya niwaju, (obinrin yii) l’o so ododo, (Yusuf) si wa ninu awon opuro

وَإِن كَانَ قَمِيصُهُ قُدَّ مِن دُبُرٍ فَكَذَبَتْ وَهُوَ مِنَ الصَّادِقِينَ(27)

 Ti o ba si je pe won fa ewu re ya leyin, (obinrin yii) l’o paro, (Yusuf) si wa ninu awon olododo

فَلَمَّا رَأَىٰ قَمِيصَهُ قُدَّ مِن دُبُرٍ قَالَ إِنَّهُ مِن كَيْدِكُنَّ ۖ إِنَّ كَيْدَكُنَّ عَظِيمٌ(28)

 Nigba ti (oko) ri ewu re ti won ti fa a ya leyin, o so pe: "Dajudaju ninu ete eyin obinrin ni (eyi). Dajudaju ete yin tobi

يُوسُفُ أَعْرِضْ عَنْ هَٰذَا ۚ وَاسْتَغْفِرِي لِذَنبِكِ ۖ إِنَّكِ كُنتِ مِنَ الْخَاطِئِينَ(29)

 Yusuf, seri kuro nibi eyi. Ki iwo (obinrin yii) si toro aforijin fun ese re. Dajudaju iwo wa lara awon alasise

۞ وَقَالَ نِسْوَةٌ فِي الْمَدِينَةِ امْرَأَتُ الْعَزِيزِ تُرَاوِدُ فَتَاهَا عَن نَّفْسِهِ ۖ قَدْ شَغَفَهَا حُبًّا ۖ إِنَّا لَنَرَاهَا فِي ضَلَالٍ مُّبِينٍ(30)

 Awon obinrin kan ninu ilu so pe: “Ayaba n jireebe fun ere ife lodo omo odo re; ife kuku ti ko si i lokan. Dajudaju awa n ri oun pe o wa ninu asise ponnbele.”

فَلَمَّا سَمِعَتْ بِمَكْرِهِنَّ أَرْسَلَتْ إِلَيْهِنَّ وَأَعْتَدَتْ لَهُنَّ مُتَّكَأً وَآتَتْ كُلَّ وَاحِدَةٍ مِّنْهُنَّ سِكِّينًا وَقَالَتِ اخْرُجْ عَلَيْهِنَّ ۖ فَلَمَّا رَأَيْنَهُ أَكْبَرْنَهُ وَقَطَّعْنَ أَيْدِيَهُنَّ وَقُلْنَ حَاشَ لِلَّهِ مَا هَٰذَا بَشَرًا إِنْ هَٰذَا إِلَّا مَلَكٌ كَرِيمٌ(31)

 Nigba ti (ayaba) gbo ete (oro) won (ti won n so nipa re), o ranse si won. O si pese ohun jije ajokooje sile fun won. O fun ikookan won ni obe (ti o maa fi jeun). O si so pe: “Jade si won, (Yusuf).” Nigba ti won ri i, won gbe e tobi (fun ewa ara re). Won si rera won lowo (fun iyanu ewa ara re). Won si wi pe: “Mimo ni fun Allahu! Eyi ki i se abara. Ki ni eyi bi ko se molaika alapon-onle.”

قَالَتْ فَذَٰلِكُنَّ الَّذِي لُمْتُنَّنِي فِيهِ ۖ وَلَقَدْ رَاوَدتُّهُ عَن نَّفْسِهِ فَاسْتَعْصَمَ ۖ وَلَئِن لَّمْ يَفْعَلْ مَا آمُرُهُ لَيُسْجَنَنَّ وَلَيَكُونًا مِّنَ الصَّاغِرِينَ(32)

 (Ayaba) so pe: “Iyen ni eni ti e bu mi fun. Dajudaju mo jireebe fun ere ife lodo re, o si wa isora. Dajudaju ti ko ba se ohun ti mo n pa lase fun un, won kuku maa fi sinu ogba ewon ni. Dajudaju o si maa wa ninu awon eni yepere.”

قَالَ رَبِّ السِّجْنُ أَحَبُّ إِلَيَّ مِمَّا يَدْعُونَنِي إِلَيْهِ ۖ وَإِلَّا تَصْرِفْ عَنِّي كَيْدَهُنَّ أَصْبُ إِلَيْهِنَّ وَأَكُن مِّنَ الْجَاهِلِينَ(33)

 (Yusuf) so pe: “Oluwa (Eledaa) mi, ogba ewon ni mo nifee si ju ohun ti won n pe mi si. Ti O o ba si seri ete won kuro lodo mi, emi yoo ko sinu ete won, emi yo si wa lara awon alaimokan.”

فَاسْتَجَابَ لَهُ رَبُّهُ فَصَرَفَ عَنْهُ كَيْدَهُنَّ ۚ إِنَّهُ هُوَ السَّمِيعُ الْعَلِيمُ(34)

 Nitori naa, Oluwa re jepe re. O si seri ete won kuro lodo re. Dajudaju Allahu, Oun ni Olugbo, Onimo

ثُمَّ بَدَا لَهُم مِّن بَعْدِ مَا رَأَوُا الْآيَاتِ لَيَسْجُنُنَّهُ حَتَّىٰ حِينٍ(35)

 Leyin igba ti won ti ri awon ami (pe Yusuf ko jebi esun), leyin naa, o han si won pe awon gbodo so o sinu ogba ewon titi di asiko kan na

وَدَخَلَ مَعَهُ السِّجْنَ فَتَيَانِ ۖ قَالَ أَحَدُهُمَا إِنِّي أَرَانِي أَعْصِرُ خَمْرًا ۖ وَقَالَ الْآخَرُ إِنِّي أَرَانِي أَحْمِلُ فَوْقَ رَأْسِي خُبْزًا تَأْكُلُ الطَّيْرُ مِنْهُ ۖ نَبِّئْنَا بِتَأْوِيلِهِ ۖ إِنَّا نَرَاكَ مِنَ الْمُحْسِنِينَ(36)

 Awon odokunrin meji kan wo inu ogba ewon pelu re. Okan ninu awon mejeeji so pe: “Emi lalaa ri ara mi pe mo n fun oti.” Eni keji so pe: “Dajudaju emi lalaa ri ara mi pe mo gbe buredi ru sori mi, eye si n je ninu re.” So itumo re fun wa. Dajudaju awa n ri o pe o wa ninu awon eni rere

قَالَ لَا يَأْتِيكُمَا طَعَامٌ تُرْزَقَانِهِ إِلَّا نَبَّأْتُكُمَا بِتَأْوِيلِهِ قَبْلَ أَن يَأْتِيَكُمَا ۚ ذَٰلِكُمَا مِمَّا عَلَّمَنِي رَبِّي ۚ إِنِّي تَرَكْتُ مِلَّةَ قَوْمٍ لَّا يُؤْمِنُونَ بِاللَّهِ وَهُم بِالْآخِرَةِ هُمْ كَافِرُونَ(37)

 O so pe: "Ounje ti won n pese fun yin ko ni ti i de ba yin, afi ki emi ti so itumo re fun eyin mejeeji siwaju ki o to de ba yin. Iyen wa ninu nnkan ti Oluwa mi fi mo mi. Dajudaju emi fi esin awon eniyan ti ko gbagbo ninu Allahu sile. Awon si ni alaigbagbo ninu Ojo Ikeyin

وَاتَّبَعْتُ مِلَّةَ آبَائِي إِبْرَاهِيمَ وَإِسْحَاقَ وَيَعْقُوبَ ۚ مَا كَانَ لَنَا أَن نُّشْرِكَ بِاللَّهِ مِن شَيْءٍ ۚ ذَٰلِكَ مِن فَضْلِ اللَّهِ عَلَيْنَا وَعَلَى النَّاسِ وَلَٰكِنَّ أَكْثَرَ النَّاسِ لَا يَشْكُرُونَ(38)

 Mo si tele esin awon baba mi, (awon Anabi) ’Ibrohim, ’Ishaƙ ati Ya‘ƙub. Ko to si wa pe ki a so nnkan kan di akegbe fun Allahu. Iyen wa ninu oore ajulo Allahu lori awa ati lori awon eniyan, sugbon opolopo awon eniyan ki i dupe (fun Allahu)

يَا صَاحِبَيِ السِّجْنِ أَأَرْبَابٌ مُّتَفَرِّقُونَ خَيْرٌ أَمِ اللَّهُ الْوَاحِدُ الْقَهَّارُ(39)

 Eyin akegbe mi mejeeji ninu ewon, se awon oluwa otooto l’o loore julo (lati josin fun) tabi Allahu, Okan soso, Olubori

مَا تَعْبُدُونَ مِن دُونِهِ إِلَّا أَسْمَاءً سَمَّيْتُمُوهَا أَنتُمْ وَآبَاؤُكُم مَّا أَنزَلَ اللَّهُ بِهَا مِن سُلْطَانٍ ۚ إِنِ الْحُكْمُ إِلَّا لِلَّهِ ۚ أَمَرَ أَلَّا تَعْبُدُوا إِلَّا إِيَّاهُ ۚ ذَٰلِكَ الدِّينُ الْقَيِّمُ وَلَٰكِنَّ أَكْثَرَ النَّاسِ لَا يَعْلَمُونَ(40)

 Ko si ohun kan ti e n josin fun leyin Re bi ko se awon oruko kan ti e so won - eyin ati awon baba yin - Allahu ko so eri kan kale fun un. Idajo (ta ni ijosin to si) ko si fun eni kan afi Allahu. O si ti pase pe e ma josin fun kini kan afi Oun nikan. Iyen ni esin t’o fese rinle, sugbon opolopo awon eniyan ko mo

يَا صَاحِبَيِ السِّجْنِ أَمَّا أَحَدُكُمَا فَيَسْقِي رَبَّهُ خَمْرًا ۖ وَأَمَّا الْآخَرُ فَيُصْلَبُ فَتَأْكُلُ الطَّيْرُ مِن رَّأْسِهِ ۚ قُضِيَ الْأَمْرُ الَّذِي فِيهِ تَسْتَفْتِيَانِ(41)

 Eyin akegbe mi mejeeji ninu ewon, ni ti eni kan ninu yin, o maa fun oga re ni oti mu. Ni ti eni keji, won yoo kan an mo igi, eye yo si maa je ninu ori re. Won ti pari oro ti eyin mejeeji n se ibeere nipa re

وَقَالَ لِلَّذِي ظَنَّ أَنَّهُ نَاجٍ مِّنْهُمَا اذْكُرْنِي عِندَ رَبِّكَ فَأَنسَاهُ الشَّيْطَانُ ذِكْرَ رَبِّهِ فَلَبِثَ فِي السِّجْنِ بِضْعَ سِنِينَ(42)

 O si so fun eni ti o ro pe o maa la ninu awon mejeeji pe: “Ranti mi lodo oga re.” Esu si mu (Yusuf) gbagbe iranti Oluwa re (nipa wiwa iranlowo sodo oga re). Nitori naa, o wa ninu ogba ewon fun awon odun die

وَقَالَ الْمَلِكُ إِنِّي أَرَىٰ سَبْعَ بَقَرَاتٍ سِمَانٍ يَأْكُلُهُنَّ سَبْعٌ عِجَافٌ وَسَبْعَ سُنبُلَاتٍ خُضْرٍ وَأُخَرَ يَابِسَاتٍ ۖ يَا أَيُّهَا الْمَلَأُ أَفْتُونِي فِي رُؤْيَايَ إِن كُنتُمْ لِلرُّؤْيَا تَعْبُرُونَ(43)

 Oba so pe: “Dajudaju emi lalaa ri maalu meje t’o sanra. Awon maalu meje t’o ru si n je won. (Mo tun lalaa ri) siri meje tutu ati omiran gbigbe. Eyin ijoye, e fun mi ni alaye itumo ala mi ti e ba je eni t’o maa n tumo ala.”

قَالُوا أَضْغَاثُ أَحْلَامٍ ۖ وَمَا نَحْنُ بِتَأْوِيلِ الْأَحْلَامِ بِعَالِمِينَ(44)

 Won so pe: “Awon ala t’o lopo mora won (niyi). Ati pe awa ki i se onimo nipa itumo awon ala.”

وَقَالَ الَّذِي نَجَا مِنْهُمَا وَادَّكَرَ بَعْدَ أُمَّةٍ أَنَا أُنَبِّئُكُم بِتَأْوِيلِهِ فَأَرْسِلُونِ(45)

 Eni ti o la ninu awon (elewon) mejeeji so pe, - o ranti (Yusuf) leyin igba pipe -: “Emi yoo fun yin ni iro nipa itumo re. Nitori naa, e fi ise ran mi na (ki ng lo se iwadii re).”

يُوسُفُ أَيُّهَا الصِّدِّيقُ أَفْتِنَا فِي سَبْعِ بَقَرَاتٍ سِمَانٍ يَأْكُلُهُنَّ سَبْعٌ عِجَافٌ وَسَبْعِ سُنبُلَاتٍ خُضْرٍ وَأُخَرَ يَابِسَاتٍ لَّعَلِّي أَرْجِعُ إِلَى النَّاسِ لَعَلَّهُمْ يَعْلَمُونَ(46)

 Yusuf, iwo olododo, fun wa ni alaye itumo ala (yii): maalu meje t’o sanra. Awon maalu meje t’o ru si n je won. Ati siri meje tutu ati omiran gbigbe. (Ki ni itumo re) nitori ki ng le fi abo sodo awon eniyan ati nitori ki won le mo (itumo re)

قَالَ تَزْرَعُونَ سَبْعَ سِنِينَ دَأَبًا فَمَا حَصَدتُّمْ فَذَرُوهُ فِي سُنبُلِهِ إِلَّا قَلِيلًا مِّمَّا تَأْكُلُونَ(47)

 O so pe: “Eyin yoo gbin nnkan ogbin fun odun meje gbako (gege bi) ise (yin). Ohunkohun ti e ba ko lere oko, ki e fi sile sinu siri re afi die ti e maa je ninu re

ثُمَّ يَأْتِي مِن بَعْدِ ذَٰلِكَ سَبْعٌ شِدَادٌ يَأْكُلْنَ مَا قَدَّمْتُمْ لَهُنَّ إِلَّا قَلِيلًا مِّمَّا تُحْصِنُونَ(48)

 Leyin naa, odun meje t’o le (fun oda ojo) yoo de leyin iyen, (awon ara ilu) yo si le je ohun ti e ti (ko lere oko) siwaju afi die ti e maa fi pamo (fun gbigbin)

ثُمَّ يَأْتِي مِن بَعْدِ ذَٰلِكَ عَامٌ فِيهِ يُغَاثُ النَّاسُ وَفِيهِ يَعْصِرُونَ(49)

 Leyin naa, odun kan ti Won yoo rojo fun awon eniyan yoo de leyin iyen. Awon eniyan yo si maa fun eso ati wara mu ninu odun naa

وَقَالَ الْمَلِكُ ائْتُونِي بِهِ ۖ فَلَمَّا جَاءَهُ الرَّسُولُ قَالَ ارْجِعْ إِلَىٰ رَبِّكَ فَاسْأَلْهُ مَا بَالُ النِّسْوَةِ اللَّاتِي قَطَّعْنَ أَيْدِيَهُنَّ ۚ إِنَّ رَبِّي بِكَيْدِهِنَّ عَلِيمٌ(50)

 Oba so pe: “E mu (Yusuf) wa fun mi.” Nigba ti iranse naa de odo re. (Yusuf) so pe: “Pada sodo oga re, ki o bi i leere pe, ki ni o sele si awon obinrin ti won re owo ara won. Dajudaju Oluwa mi ni Onimo nipa ete won.”

قَالَ مَا خَطْبُكُنَّ إِذْ رَاوَدتُّنَّ يُوسُفَ عَن نَّفْسِهِ ۚ قُلْنَ حَاشَ لِلَّهِ مَا عَلِمْنَا عَلَيْهِ مِن سُوءٍ ۚ قَالَتِ امْرَأَتُ الْعَزِيزِ الْآنَ حَصْحَصَ الْحَقُّ أَنَا رَاوَدتُّهُ عَن نَّفْسِهِ وَإِنَّهُ لَمِنَ الصَّادِقِينَ(51)

 (Oba) so pe: "Ki ni oro tiyin ti je ti e fi jireebe fun ere ife lodo Yusuf?" Won so pe: “Mimo ni fun Allahu. awa ko mo aburu kan mo Yusuf.” Ayaba so pe: “Nisinsin yii ni ododo foju han. Emi ni mo jireebe fun ere ife lodo re. Dajudaju o wa ninu awon olododo.”

ذَٰلِكَ لِيَعْلَمَ أَنِّي لَمْ أَخُنْهُ بِالْغَيْبِ وَأَنَّ اللَّهَ لَا يَهْدِي كَيْدَ الْخَائِنِينَ(52)

 (Yusuf so pe): "Iyen nitori ki oba le mo pe dajudaju emi ko janba re ni ikoko. Ati pe dajudaju Allahu ko nii fi imona sibi ete awon onijanba

۞ وَمَا أُبَرِّئُ نَفْسِي ۚ إِنَّ النَّفْسَ لَأَمَّارَةٌ بِالسُّوءِ إِلَّا مَا رَحِمَ رَبِّي ۚ إِنَّ رَبِّي غَفُورٌ رَّحِيمٌ(53)

 Emi ko si fora mi mo (nibi erokero); dajudaju emi kuku n pase erokero (fun eda) ni afi eni ti Oluwa mi ba ke. Dajudaju Oluwa mi ni Alaforijin, Asake-orun

وَقَالَ الْمَلِكُ ائْتُونِي بِهِ أَسْتَخْلِصْهُ لِنَفْسِي ۖ فَلَمَّا كَلَّمَهُ قَالَ إِنَّكَ الْيَوْمَ لَدَيْنَا مَكِينٌ أَمِينٌ(54)

 Oba so pe: “E mu (Yusuf) wa fun mi. Emi yoo se e ni eni esa lodo mi.” Nigba ti oba ba a soro tan, o so pe: “Lodo wa ni oni dajudaju iwo ni eni pataki, olufokantan.”

قَالَ اجْعَلْنِي عَلَىٰ خَزَائِنِ الْأَرْضِ ۖ إِنِّي حَفِيظٌ عَلِيمٌ(55)

 (Yusuf) so pe: “Fi mi se alase awon oro ilu, dajudaju alamojuuto onimo ni mi.”

وَكَذَٰلِكَ مَكَّنَّا لِيُوسُفَ فِي الْأَرْضِ يَتَبَوَّأُ مِنْهَا حَيْثُ يَشَاءُ ۚ نُصِيبُ بِرَحْمَتِنَا مَن نَّشَاءُ ۖ وَلَا نُضِيعُ أَجْرَ الْمُحْسِنِينَ(56)

 Bayen ni A se fun Yusuf ni ipo ati ibugbe lori ile. O si n gbe ni ibi ti o ba fe. Awa n mu ike Wa ba enikeni ti A ba fe. A o si nii fi esan awon oluse-rere rare

وَلَأَجْرُ الْآخِرَةِ خَيْرٌ لِّلَّذِينَ آمَنُوا وَكَانُوا يَتَّقُونَ(57)

 Dajudaju esan ti orun loore julo fun awon t’o gbagbo ni ododo, ti won si n beru (Allahu)

وَجَاءَ إِخْوَةُ يُوسُفَ فَدَخَلُوا عَلَيْهِ فَعَرَفَهُمْ وَهُمْ لَهُ مُنكِرُونَ(58)

 Awon obakan (Anabi) Yusuf de, won si wole to o. O da won mo. Awon ko si mo on mo

وَلَمَّا جَهَّزَهُم بِجَهَازِهِمْ قَالَ ائْتُونِي بِأَخٍ لَّكُم مِّنْ أَبِيكُمْ ۚ أَلَا تَرَوْنَ أَنِّي أُوفِي الْكَيْلَ وَأَنَا خَيْرُ الْمُنزِلِينَ(59)

 Nigba ti o si ba won di eru ounje won tan, o so pe: "E lo mu obakan yin wa lati odo baba yin. Se e ko ri i pe dajudaju mo n won kongo ni ekun rere ni? Emi si dara julo ninu awon olugbalejo

فَإِن لَّمْ تَأْتُونِي بِهِ فَلَا كَيْلَ لَكُمْ عِندِي وَلَا تَقْرَبُونِ(60)

 Ti e o ba si mu un wa, ko si (eru ounje) wiwon fun yin lodo mi. Ki e si ma se sunmo mi

قَالُوا سَنُرَاوِدُ عَنْهُ أَبَاهُ وَإِنَّا لَفَاعِلُونَ(61)

 Won so pe: “A maa jireebe fun un lodo baba re. Dajudaju awa maa se bee.”

وَقَالَ لِفِتْيَانِهِ اجْعَلُوا بِضَاعَتَهُمْ فِي رِحَالِهِمْ لَعَلَّهُمْ يَعْرِفُونَهَا إِذَا انقَلَبُوا إِلَىٰ أَهْلِهِمْ لَعَلَّهُمْ يَرْجِعُونَ(62)

 O si so fun awon omo odo re pe: “E fi owo-oja won sinu eru (ounje) won nitori ki won le mo nigba ti won ba pada de odo ara ile won (pe a ti da a pada fun won), won yo si le pada wa.”

فَلَمَّا رَجَعُوا إِلَىٰ أَبِيهِمْ قَالُوا يَا أَبَانَا مُنِعَ مِنَّا الْكَيْلُ فَأَرْسِلْ مَعَنَا أَخَانَا نَكْتَلْ وَإِنَّا لَهُ لَحَافِظُونَ(63)

 Nigba ti won pada de odo baba won, won so pe: “Baba wa, won ko lati won ounje fun wa. Nitori naa, je ki obakan wa ba wa lo nitori ki a le ri ounje won (wale). Dajudaju awa ni oluso fun un.”

قَالَ هَلْ آمَنُكُمْ عَلَيْهِ إِلَّا كَمَا أَمِنتُكُمْ عَلَىٰ أَخِيهِ مِن قَبْلُ ۖ فَاللَّهُ خَيْرٌ حَافِظًا ۖ وَهُوَ أَرْحَمُ الرَّاحِمِينَ(64)

 O so pe: “Se ki ng gba yin gbo lori re bi ko se bi mo se gba yin gbo ni isaaju lori omo-iya re? Nitori naa, Allahu loore julo ni Oluso. Oun si ni Alaaanu-julo ninu awon alaaanu.”

وَلَمَّا فَتَحُوا مَتَاعَهُمْ وَجَدُوا بِضَاعَتَهُمْ رُدَّتْ إِلَيْهِمْ ۖ قَالُوا يَا أَبَانَا مَا نَبْغِي ۖ هَٰذِهِ بِضَاعَتُنَا رُدَّتْ إِلَيْنَا ۖ وَنَمِيرُ أَهْلَنَا وَنَحْفَظُ أَخَانَا وَنَزْدَادُ كَيْلَ بَعِيرٍ ۖ ذَٰلِكَ كَيْلٌ يَسِيرٌ(65)

 Nigba ti won tu eru ounje won, won ri owo-oja won ti won da pada fun won (ninu re). Won so pe: “Baba wa, ki ni a tun n fe? Owo-oja wa niyi ti won ti da pada fun wa. A o si tun fi wa ounje ra fun awon ebi wa. A o si daabo bo obakan wa. A si maa ri alekun eru ounje (ti) rakunmi kan le ru si i. Iwon ounje kekere si niyen (lodo oba).”

قَالَ لَنْ أُرْسِلَهُ مَعَكُمْ حَتَّىٰ تُؤْتُونِ مَوْثِقًا مِّنَ اللَّهِ لَتَأْتُنَّنِي بِهِ إِلَّا أَن يُحَاطَ بِكُمْ ۖ فَلَمَّا آتَوْهُ مَوْثِقَهُمْ قَالَ اللَّهُ عَلَىٰ مَا نَقُولُ وَكِيلٌ(66)

 O so pe: “Emi ko nii je ki o ba yin lo titi e maa fi se adehun fun mi ni (oruko) Allahu pe dajudaju e maa mu un pada wa ba mi afi ti (awon ota) ba ka yin mo.” Nigba ti won fun un ni adehun won tan, o so pe: “Allahu ni Elerii lori ohun ti a n so (yii).”

وَقَالَ يَا بَنِيَّ لَا تَدْخُلُوا مِن بَابٍ وَاحِدٍ وَادْخُلُوا مِنْ أَبْوَابٍ مُّتَفَرِّقَةٍ ۖ وَمَا أُغْنِي عَنكُم مِّنَ اللَّهِ مِن شَيْءٍ ۖ إِنِ الْحُكْمُ إِلَّا لِلَّهِ ۖ عَلَيْهِ تَوَكَّلْتُ ۖ وَعَلَيْهِ فَلْيَتَوَكَّلِ الْمُتَوَكِّلُونَ(67)

 O tun so pe: “Eyin omo mi, e ma se gba enu ona eyo kan wole. E gba enu ona otooto wole. Emi ko le fi nnkan kan ro yin loro lodo Allahu. Ko si idajo (fun eni kan) afi fun Allahu. Oun ni mo gbarale. Oun si ni ki awon olugbarale gbarale.”

وَلَمَّا دَخَلُوا مِنْ حَيْثُ أَمَرَهُمْ أَبُوهُم مَّا كَانَ يُغْنِي عَنْهُم مِّنَ اللَّهِ مِن شَيْءٍ إِلَّا حَاجَةً فِي نَفْسِ يَعْقُوبَ قَضَاهَا ۚ وَإِنَّهُ لَذُو عِلْمٍ لِّمَا عَلَّمْنَاهُ وَلَٰكِنَّ أَكْثَرَ النَّاسِ لَا يَعْلَمُونَ(68)

 Nigba ti won wo (inu ilu) ni awon aye ti baba won pa lase fun won, ko si ro won loro kan kan lodo Allahu bi ko se bukata kan ninu emi (Anabi) Ya‘ƙub ti o muse. Dajudaju onimo ni nipa ohun ti A fi mo on, sugbon opolopo awon eniyan ko mo

وَلَمَّا دَخَلُوا عَلَىٰ يُوسُفَ آوَىٰ إِلَيْهِ أَخَاهُ ۖ قَالَ إِنِّي أَنَا أَخُوكَ فَلَا تَبْتَئِسْ بِمَا كَانُوا يَعْمَلُونَ(69)

 Nigba ti won wole ti (Anabi) Yusuf, o mu omo-iya re mora sodo re. O so pe: “Dajudaju emi ni omo-iya re. Nitori naa, ma se banuje nipa ohun ti won n se nise.”

فَلَمَّا جَهَّزَهُم بِجَهَازِهِمْ جَعَلَ السِّقَايَةَ فِي رَحْلِ أَخِيهِ ثُمَّ أَذَّنَ مُؤَذِّنٌ أَيَّتُهَا الْعِيرُ إِنَّكُمْ لَسَارِقُونَ(70)

 Nigba ti o si ba won di eru won tan, o fi ife-imumi sinu eru omo-iya re. Leyin naa, olupepe kan kede pe: “Eyin ero-rakunmi, dajudaju eyin ni ole.”

قَالُوا وَأَقْبَلُوا عَلَيْهِم مَّاذَا تَفْقِدُونَ(71)

 Won doju ko won, won so pe: “Ki l’e safeku?”

قَالُوا نَفْقِدُ صُوَاعَ الْمَلِكِ وَلِمَن جَاءَ بِهِ حِمْلُ بَعِيرٍ وَأَنَا بِهِ زَعِيمٌ(72)

 Won so pe: “A o ri ife oba ni. Eni ti o ba si mu un wa yoo ri eru ounje rakunmi kan gba. Emi si ni oniduroo fun ebun naa.”

قَالُوا تَاللَّهِ لَقَدْ عَلِمْتُم مَّا جِئْنَا لِنُفْسِدَ فِي الْأَرْضِ وَمَا كُنَّا سَارِقِينَ(73)

 Won so pe: “A fi Allahu bura, dajudaju e mo pe a ko wa lati sebaje lori ile. Ati pe awa ki i se ole.”

قَالُوا فَمَا جَزَاؤُهُ إِن كُنتُمْ كَاذِبِينَ(74)

 Won so pe: “Ki ni esan (fun eni ti) o ji i, ti (o ba han pe) eyin je opuro?”

قَالُوا جَزَاؤُهُ مَن وُجِدَ فِي رَحْلِهِ فَهُوَ جَزَاؤُهُ ۚ كَذَٰلِكَ نَجْزِي الظَّالِمِينَ(75)

 Won so pe: “Esan re; eni ti won ba ba a ninu eru re, oun naa ni esan re. Bayen ni awa naa se n san awon alabosi ni esan.”

فَبَدَأَ بِأَوْعِيَتِهِمْ قَبْلَ وِعَاءِ أَخِيهِ ثُمَّ اسْتَخْرَجَهَا مِن وِعَاءِ أَخِيهِ ۚ كَذَٰلِكَ كِدْنَا لِيُوسُفَ ۖ مَا كَانَ لِيَأْخُذَ أَخَاهُ فِي دِينِ الْمَلِكِ إِلَّا أَن يَشَاءَ اللَّهُ ۚ نَرْفَعُ دَرَجَاتٍ مَّن نَّشَاءُ ۗ وَفَوْقَ كُلِّ ذِي عِلْمٍ عَلِيمٌ(76)

 O si bere (ayewo) apo won siwaju apo omo-iya re. Leyin naa, o mu un jade lati inu apo omo-iya re. Bayen ni A se fun (Anabi) Yusuf ni ete da. Ko le fi ofin oba mu omo-iya re afi ti Allahu ba fe. A n sagbega fun enikeni ti A ba fe. Onimo wa loke gbogbo onimo

۞ قَالُوا إِن يَسْرِقْ فَقَدْ سَرَقَ أَخٌ لَّهُ مِن قَبْلُ ۚ فَأَسَرَّهَا يُوسُفُ فِي نَفْسِهِ وَلَمْ يُبْدِهَا لَهُمْ ۚ قَالَ أَنتُمْ شَرٌّ مَّكَانًا ۖ وَاللَّهُ أَعْلَمُ بِمَا تَصِفُونَ(77)

 Won so pe: “Ti o ba jale, dajudaju omo-iya re kan ti jale siwaju.” (Anabi) Yusuf si fi oro naa pamo sinu emi re, ko si fi han si won pe (ko ri bee). O (si) so pe: “Ipo tiyin l’o buru julo. Allahu l’O si nimo julo nipa ohun ti e n so.”

قَالُوا يَا أَيُّهَا الْعَزِيزُ إِنَّ لَهُ أَبًا شَيْخًا كَبِيرًا فَخُذْ أَحَدَنَا مَكَانَهُ ۖ إِنَّا نَرَاكَ مِنَ الْمُحْسِنِينَ(78)

 Won so pe: "Iwo oba, dajudaju o ni baba arugbo agbalagba kan. Nitori naa, mu eni kan ninu wa dipo re. Dajudaju awa n ri iwo pe o wa ninu awon eni-rere

قَالَ مَعَاذَ اللَّهِ أَن نَّأْخُذَ إِلَّا مَن وَجَدْنَا مَتَاعَنَا عِندَهُ إِنَّا إِذًا لَّظَالِمُونَ(79)

 O so pe: “Mo sadi Allahu pe ki a mu eni kan afi eni ti a ba eru wa lodo re. (Ti a ba mu elomiiran) dajudaju nigba naa alabosi ni wa.”

فَلَمَّا اسْتَيْأَسُوا مِنْهُ خَلَصُوا نَجِيًّا ۖ قَالَ كَبِيرُهُمْ أَلَمْ تَعْلَمُوا أَنَّ أَبَاكُمْ قَدْ أَخَذَ عَلَيْكُم مَّوْثِقًا مِّنَ اللَّهِ وَمِن قَبْلُ مَا فَرَّطتُمْ فِي يُوسُفَ ۖ فَلَنْ أَبْرَحَ الْأَرْضَ حَتَّىٰ يَأْذَنَ لِي أَبِي أَوْ يَحْكُمَ اللَّهُ لِي ۖ وَهُوَ خَيْرُ الْحَاكِمِينَ(80)

 Nigba ti won soreti nu nipa re, won te soro. Agba (ninu) won so pe: “Se e ko mo pe dajudaju baba yin ti gba adehun yin ti (e se ni oruko) Allahu. Ati pe siwaju (eyi, e ti se) aseeto nipa oro (Anabi) Yusuf. Nitori naa, emi ko nii fi ile (Misro) sile titi baba mi yoo fi yonda fun mi tabi (titi) Allahu yoo fi se idajo fun mi. O si loore julo ninu awon oludajo

ارْجِعُوا إِلَىٰ أَبِيكُمْ فَقُولُوا يَا أَبَانَا إِنَّ ابْنَكَ سَرَقَ وَمَا شَهِدْنَا إِلَّا بِمَا عَلِمْنَا وَمَا كُنَّا لِلْغَيْبِ حَافِظِينَ(81)

 E pada sodo baba yin, ki e si so pe: “Baba wa, dajudaju omo re jale. A ko si le jerii (si kini kan) afi ohun ti a ba nimo (nipa) re. Awa ko si je oluso fun ohun ti o pamo (fun wa)

وَاسْأَلِ الْقَرْيَةَ الَّتِي كُنَّا فِيهَا وَالْعِيرَ الَّتِي أَقْبَلْنَا فِيهَا ۖ وَإِنَّا لَصَادِقُونَ(82)

 Ki o si bi awon ara ilu ti a wa ninu re ati ero-rakunmi ti a jo dari de leere wo. Dajudaju olododo ma ni wa.”

قَالَ بَلْ سَوَّلَتْ لَكُمْ أَنفُسُكُمْ أَمْرًا ۖ فَصَبْرٌ جَمِيلٌ ۖ عَسَى اللَّهُ أَن يَأْتِيَنِي بِهِمْ جَمِيعًا ۚ إِنَّهُ هُوَ الْعَلِيمُ الْحَكِيمُ(83)

 (Anabi Ya‘ƙub) so pe: “Rara o, emi yin lo se oran kan losoo fun yin. Nitori naa, suuru t’o rewa (loro mi kan bayii). O see se ki Allahu ba mi mu gbogbo won wa. Dajudaju Allahu, Oun ni Onimo, Ologbon.”

وَتَوَلَّىٰ عَنْهُمْ وَقَالَ يَا أَسَفَىٰ عَلَىٰ يُوسُفَ وَابْيَضَّتْ عَيْنَاهُ مِنَ الْحُزْنِ فَهُوَ كَظِيمٌ(84)

 O pa won ti, o si so pe: “Ibanuje n be fun mi lori Yusuf!” Oju re mejeeji si funfun wa (ko si riran mo); o si pa ibanuje mora

قَالُوا تَاللَّهِ تَفْتَأُ تَذْكُرُ يُوسُفَ حَتَّىٰ تَكُونَ حَرَضًا أَوْ تَكُونَ مِنَ الْهَالِكِينَ(85)

 Won so pe: “A fi Allahu bura, iwo ko ye ranti Yusuf titi o maa fi di yannayanna tabi (titi) o maa fi di ara awon oku.”

قَالَ إِنَّمَا أَشْكُو بَثِّي وَحُزْنِي إِلَى اللَّهِ وَأَعْلَمُ مِنَ اللَّهِ مَا لَا تَعْلَمُونَ(86)

 O so pe: “Allahu ma ni emi n ro edun okan mi ati ibanuje mi fun. Mo si mo ohun ti e ko mo nipa Allahu

يَا بَنِيَّ اذْهَبُوا فَتَحَسَّسُوا مِن يُوسُفَ وَأَخِيهِ وَلَا تَيْأَسُوا مِن رَّوْحِ اللَّهِ ۖ إِنَّهُ لَا يَيْأَسُ مِن رَّوْحِ اللَّهِ إِلَّا الْقَوْمُ الْكَافِرُونَ(87)

 Eyin omo mi, e lo wadii nipa Yusuf ati omo-iya re. E si ma se soreti nu ninu ike Allahu. Dajudaju ko si eni kan ti o maa soreti nu ninu ike Allahu afi ijo alaigbagbo.”

فَلَمَّا دَخَلُوا عَلَيْهِ قَالُوا يَا أَيُّهَا الْعَزِيزُ مَسَّنَا وَأَهْلَنَا الضُّرُّ وَجِئْنَا بِبِضَاعَةٍ مُّزْجَاةٍ فَأَوْفِ لَنَا الْكَيْلَ وَتَصَدَّقْ عَلَيْنَا ۖ إِنَّ اللَّهَ يَجْزِي الْمُتَصَدِّقِينَ(88)

 Nigba ti won wole to Yusuf, won so pe: “Iwo oba, inira ti mu awa ati ara ile wa. A si mu owo kan ti ko yanju wa. Nitori naa, won kongo (ounje) naa kun fun wa, ki o si ta wa lore. Dajudaju Allahu yoo san awon olutore ni esan rere.”

قَالَ هَلْ عَلِمْتُم مَّا فَعَلْتُم بِيُوسُفَ وَأَخِيهِ إِذْ أَنتُمْ جَاهِلُونَ(89)

 O so pe: “Nje e mo ohun ti e se fun Yusuf ati omo-iya re nigba ti eyin je alaimokan.”

قَالُوا أَإِنَّكَ لَأَنتَ يُوسُفُ ۖ قَالَ أَنَا يُوسُفُ وَهَٰذَا أَخِي ۖ قَدْ مَنَّ اللَّهُ عَلَيْنَا ۖ إِنَّهُ مَن يَتَّقِ وَيَصْبِرْ فَإِنَّ اللَّهَ لَا يُضِيعُ أَجْرَ الْمُحْسِنِينَ(90)

 Won so pe: “Se dajudaju iwo ni Yusuf?” O so pe: “Emi ni Yusuf. Omo-iya mi si niyi. Dajudaju Allahu ti se idera fun wa. Dajudaju enikeni ti o ba beru (Allahu), ti o si se suuru, dajudaju Allahu ko nii fi esan awon oluse-rere rare.”

قَالُوا تَاللَّهِ لَقَدْ آثَرَكَ اللَّهُ عَلَيْنَا وَإِن كُنَّا لَخَاطِئِينَ(91)

 Won so pe: “A fi Allahu bura! Dajudaju Allahu ti gbola fun o ju wa lo. Ati pe dajudaju awa ni alasise.”

قَالَ لَا تَثْرِيبَ عَلَيْكُمُ الْيَوْمَ ۖ يَغْفِرُ اللَّهُ لَكُمْ ۖ وَهُوَ أَرْحَمُ الرَّاحِمِينَ(92)

 O so pe: "Ko si ibawi fun yin ni oni. Allahu yoo forijin yin. Oun si ni Alaaanu-julo ninu awon alaaanu

اذْهَبُوا بِقَمِيصِي هَٰذَا فَأَلْقُوهُ عَلَىٰ وَجْهِ أَبِي يَأْتِ بَصِيرًا وَأْتُونِي بِأَهْلِكُمْ أَجْمَعِينَ(93)

 E mu ewu mi yii lo, ki e fi le iwaju baba mi, o maa pada di oluriran. Ki e si ko gbogbo ebi yin wa ba mi

وَلَمَّا فَصَلَتِ الْعِيرُ قَالَ أَبُوهُمْ إِنِّي لَأَجِدُ رِيحَ يُوسُفَ ۖ لَوْلَا أَن تُفَنِّدُونِ(94)

 Nigba ti ero-rakunmi naa si pinya (kuro lodo Anabi Yusuf), baba won so pe: “Dajudaju emi n gbo oorun Yusuf ti e o ba nii so pe mo n jaran.”

قَالُوا تَاللَّهِ إِنَّكَ لَفِي ضَلَالِكَ الْقَدِيمِ(95)

 Won so pe: “A fi Allahu bura! Dajudaju iwo si wa ninu asise re ti atijo (nipa ife Yusuf).”

فَلَمَّا أَن جَاءَ الْبَشِيرُ أَلْقَاهُ عَلَىٰ وَجْهِهِ فَارْتَدَّ بَصِيرًا ۖ قَالَ أَلَمْ أَقُل لَّكُمْ إِنِّي أَعْلَمُ مِنَ اللَّهِ مَا لَا تَعْلَمُونَ(96)

 Nigba ti oniroo-idunnu de, o ju (ewu naa) le e niwaju, o si riran pada. O so pe: “Nje ng ko so fun yin pe dajudaju emi mo ohun ti e ko mo nipa Allahu.”

قَالُوا يَا أَبَانَا اسْتَغْفِرْ لَنَا ذُنُوبَنَا إِنَّا كُنَّا خَاطِئِينَ(97)

 Won so pe: “Baba wa, toro aforijin ese wa fun wa, dajudaju awa je alasise.”

قَالَ سَوْفَ أَسْتَغْفِرُ لَكُمْ رَبِّي ۖ إِنَّهُ هُوَ الْغَفُورُ الرَّحِيمُ(98)

 O so pe: “Laipe mo maa toro aforijin fun yin lodo Oluwa mi. Dajudaju Allahu, Oun ni Alaforijin, Asake-orun.”

فَلَمَّا دَخَلُوا عَلَىٰ يُوسُفَ آوَىٰ إِلَيْهِ أَبَوَيْهِ وَقَالَ ادْخُلُوا مِصْرَ إِن شَاءَ اللَّهُ آمِنِينَ(99)

 Nigba ti won wole to (Anabi) Yusuf, o ko awon obi re mejeeji mora sodo re, o si so pe: “E wo ilu Misro ni olufayabale – ti Allahu ba fe.-”

وَرَفَعَ أَبَوَيْهِ عَلَى الْعَرْشِ وَخَرُّوا لَهُ سُجَّدًا ۖ وَقَالَ يَا أَبَتِ هَٰذَا تَأْوِيلُ رُؤْيَايَ مِن قَبْلُ قَدْ جَعَلَهَا رَبِّي حَقًّا ۖ وَقَدْ أَحْسَنَ بِي إِذْ أَخْرَجَنِي مِنَ السِّجْنِ وَجَاءَ بِكُم مِّنَ الْبَدْوِ مِن بَعْدِ أَن نَّزَغَ الشَّيْطَانُ بَيْنِي وَبَيْنَ إِخْوَتِي ۚ إِنَّ رَبِّي لَطِيفٌ لِّمَا يَشَاءُ ۚ إِنَّهُ هُوَ الْعَلِيمُ الْحَكِيمُ(100)

 O gbe awon obi re mejeeji sori ite. Won si doju bole fun un ni oluforikanle-kini. O so pe: “Baba mi, eyi ni itumo ala mi (ti mo la) siwaju. Dajudaju Oluwa mi ti so o di ododo. O si se daadaa fun mi nigba ti O mu mi jade kuro ninu ogba ewon. O tun mu yin wa (ba mi) lati inu oko leyin ti Esu ti ba aarin emi ati awon oba-kan mi je. Dajudaju Oluwa mi ni Alaaanu fun ohun ti O ba fe. Dajudaju Allahu, Oun ni Onimo, Ologbon

۞ رَبِّ قَدْ آتَيْتَنِي مِنَ الْمُلْكِ وَعَلَّمْتَنِي مِن تَأْوِيلِ الْأَحَادِيثِ ۚ فَاطِرَ السَّمَاوَاتِ وَالْأَرْضِ أَنتَ وَلِيِّي فِي الدُّنْيَا وَالْآخِرَةِ ۖ تَوَفَّنِي مُسْلِمًا وَأَلْحِقْنِي بِالصَّالِحِينَ(101)

 Oluwa mi, dajudaju O ti fun mi ni ijoba. O tun fun mi ni imo itumo ala. Olupileda awon sanmo ati ile, Iwo ni Oluranlowo mi ni aye ati ni orun, pa mi sipo musulumi. Ki O si fi mi pelu awon eni rere.”

ذَٰلِكَ مِنْ أَنبَاءِ الْغَيْبِ نُوحِيهِ إِلَيْكَ ۖ وَمَا كُنتَ لَدَيْهِمْ إِذْ أَجْمَعُوا أَمْرَهُمْ وَهُمْ يَمْكُرُونَ(102)

 Iyen wa ninu iro ikoko ti A fi imisi (re) ranse si o. Ati pe iwo ko si lodo won nigba ti won panu po lori oro won, ti won n dete

وَمَا أَكْثَرُ النَّاسِ وَلَوْ حَرَصْتَ بِمُؤْمِنِينَ(103)

 Iwo ibaa soju kokoro (igbala won), opolopo eniyan ni ko nii gbagbo

وَمَا تَسْأَلُهُمْ عَلَيْهِ مِنْ أَجْرٍ ۚ إِنْ هُوَ إِلَّا ذِكْرٌ لِّلْعَالَمِينَ(104)

 Iwo ko si bi won leere owo-oya kan lori re. Ko si je kini kan bi ko se iranti fun gbogbo eda

وَكَأَيِّن مِّنْ آيَةٍ فِي السَّمَاوَاتِ وَالْأَرْضِ يَمُرُّونَ عَلَيْهَا وَهُمْ عَنْهَا مُعْرِضُونَ(105)

 Ati pe meloo meloo ninu awon ami ti n be ni sanmo ati ni ori ile ti won n re koja lori re, ti won si n gbunri kuro nibe

وَمَا يُؤْمِنُ أَكْثَرُهُم بِاللَّهِ إِلَّا وَهُم مُّشْرِكُونَ(106)

 Opolopo won si ni ko nii gba Allahu gbo ni ododo afi ki won tun maa sebo

أَفَأَمِنُوا أَن تَأْتِيَهُمْ غَاشِيَةٌ مِّنْ عَذَابِ اللَّهِ أَوْ تَأْتِيَهُمُ السَّاعَةُ بَغْتَةً وَهُمْ لَا يَشْعُرُونَ(107)

 Se won faya bale pe ohun ti n bo eda mole ninu iya Allahu ko le de ba awon ni tabi pe Akoko naa ko le ko le awon lori ni ojiji, ti won ko si nii fura

قُلْ هَٰذِهِ سَبِيلِي أَدْعُو إِلَى اللَّهِ ۚ عَلَىٰ بَصِيرَةٍ أَنَا وَمَنِ اتَّبَعَنِي ۖ وَسُبْحَانَ اللَّهِ وَمَا أَنَا مِنَ الْمُشْرِكِينَ(108)

 So pe: “Eyi ni oju ona (esin) mi, emi ati awon t’o tele mi si n pepe si (esin) Allahu pelu imo amodaju. Mimo ni fun Allahu. Emi ko si si lara awon osebo.”

وَمَا أَرْسَلْنَا مِن قَبْلِكَ إِلَّا رِجَالًا نُّوحِي إِلَيْهِم مِّنْ أَهْلِ الْقُرَىٰ ۗ أَفَلَمْ يَسِيرُوا فِي الْأَرْضِ فَيَنظُرُوا كَيْفَ كَانَ عَاقِبَةُ الَّذِينَ مِن قَبْلِهِمْ ۗ وَلَدَارُ الْآخِرَةِ خَيْرٌ لِّلَّذِينَ اتَّقَوْا ۗ أَفَلَا تَعْقِلُونَ(109)

 A o ran eni kan ni ise-ojise siwaju re afi awon okunrin ti A n fi imisi ranse si ninu awon ara ilu. Se won ko rin kiri lori ile ki won wo bi ikangun awon t’o siwaju won se ri? Dajudaju Ile ikeyin loore julo fun awon t’o beru (Allahu). Se e o se laakaye ni

حَتَّىٰ إِذَا اسْتَيْأَسَ الرُّسُلُ وَظَنُّوا أَنَّهُمْ قَدْ كُذِبُوا جَاءَهُمْ نَصْرُنَا فَنُجِّيَ مَن نَّشَاءُ ۖ وَلَا يُرَدُّ بَأْسُنَا عَنِ الْقَوْمِ الْمُجْرِمِينَ(110)

 (A ki i je awon eniyan niya) titi di igba ti awon Ojise ba t’o soreti nu (nipa igbagbo won), ti won si mo pe won ti pe awon ni opuro. Aranse Wa yo si de ba won. A si maa gba eni ti A ba fe la. Won ko le da iya Wa pada lori ijo elese

لَقَدْ كَانَ فِي قَصَصِهِمْ عِبْرَةٌ لِّأُولِي الْأَلْبَابِ ۗ مَا كَانَ حَدِيثًا يُفْتَرَىٰ وَلَٰكِن تَصْدِيقَ الَّذِي بَيْنَ يَدَيْهِ وَتَفْصِيلَ كُلِّ شَيْءٍ وَهُدًى وَرَحْمَةً لِّقَوْمٍ يُؤْمِنُونَ(111)

 Dajudaju ariwoye wa ninu itan won fun awon onilaakaye. (Al-Ƙur’an) ki i se oro kan ti won n hun, sugbon o n jerii si eyi t’o je ododo ninu eyi t’o siwaju re, o n salaye gbogbo nnkan; o je imona ati ike fun ijo onigbagbo ododo


More surahs in Yoruba:


Al-Baqarah Al-'Imran An-Nisa'
Al-Ma'idah Yusuf Ibrahim
Al-Hijr Al-Kahf Maryam
Al-Hajj Al-Qasas Al-'Ankabut
As-Sajdah Ya Sin Ad-Dukhan
Al-Fath Al-Hujurat Qaf
An-Najm Ar-Rahman Al-Waqi'ah
Al-Hashr Al-Mulk Al-Haqqah
Al-Inshiqaq Al-A'la Al-Ghashiyah

Download surah Yusuf with the voice of the most famous Quran reciters :

surah Yusuf mp3 : choose the reciter to listen and download the chapter Yusuf Complete with high quality
surah Yusuf Ahmed El Agamy
Ahmed Al Ajmy
surah Yusuf Bandar Balila
Bandar Balila
surah Yusuf Khalid Al Jalil
Khalid Al Jalil
surah Yusuf Saad Al Ghamdi
Saad Al Ghamdi
surah Yusuf Saud Al Shuraim
Saud Al Shuraim
surah Yusuf Abdul Basit Abdul Samad
Abdul Basit
surah Yusuf Abdul Rashid Sufi
Abdul Rashid Sufi
surah Yusuf Abdullah Basfar
Abdullah Basfar
surah Yusuf Abdullah Awwad Al Juhani
Abdullah Al Juhani
surah Yusuf Fares Abbad
Fares Abbad
surah Yusuf Maher Al Muaiqly
Maher Al Muaiqly
surah Yusuf Muhammad Siddiq Al Minshawi
Al Minshawi
surah Yusuf Al Hosary
Al Hosary
surah Yusuf Al-afasi
Mishari Al-afasi
surah Yusuf Yasser Al Dosari
Yasser Al Dosari


Saturday, May 4, 2024

لا تنسنا من دعوة صالحة بظهر الغيب